Àlàyé nípa Ètò Bíbélì

Ṣíṣe Àkóso Àkókò N'ìlànà Ọlọ́runÀpẹrẹ

Divine Time Management

Ọjọ́ 1 nínú 6

Ohun Tí Ọlọ́run Fẹ́ Ká Máa Ṣe Nígbà Tá A Bá Ń Lo Àkókò Wa

Gẹ́gẹ́ bí olùkọ́ni lórí ìṣètò àkókò láti ọdún 2009, mo ti lo apá tó pọ̀ jù nínú iṣẹ́ mi láti kọ́ àwọn èèyàn ní àwọn ọ̀nà àti èrò tó yẹ kí wọ́n máa gbà ṣe àwọn nǹkan. Lára rẹ̀ ni pé kó o mọ ohun tó yẹ kó o fi sípò àkọ́kọ́, kó o ṣètò bó o ṣe máa ṣe àwọn nǹkan, kó o sì máa bójú tó àwọn iṣẹ́. Ṣùgbọ́n lọ́dún 2015, Ọlọ́run mú kí n mọ̀ pé ó yẹ kí n bẹ̀rẹ̀ sí í fi ẹ̀sìn Kristẹni mi kún iṣẹ́ mi. Èyí mú mi lọ sí ìrìn àjò láti ṣàwárí ọ̀nà ìdarí àkókò ọlọ́run. Èrò kan tí Sáàmù 46:10a (NASB)ṣàkópọ̀ rẹ̀: "Ẹ dáwọ́ ìsapá yín dúró, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ni Ọlọ́run".

Lílo àkókò lọ́nà tó bá ìfẹ́ Ọlọ́run mu kì í wulẹ̀ ṣe pé kó o máa kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lójoojúmọ́ nìkan, àmọ́ ó tún túmọ̀ sí pé kó o máa ronú nípa àkókò lọ́nà tó yàtọ̀ pátápátá.

Ọlọ́run kò fẹ́ ká máa fi agbára wa láti ṣàkóso ara wa àti láti máa bójú tó ìgbésí ayé wa ṣe òrìṣà. Ṣùgbọ́n, ó fẹ́ ká gbẹ́kẹ̀ lé òun nínú gbogbo ohun tá a bá ń ṣe.

Bí Sáàmù 127:1-2 (NIV) ṣe rọ̀ wá pé:

Àyàfi bí Olúwa bá kọ́ ilé náà,

àwọn olùkọ́ ilé ń ṣe làálàá lásán.

Bí Olúwa kò bá ń ṣọ́ ìlú,

asán ni àwọn olùṣọ́ ń ṣọ́nà.

Asán ni ẹ̀yin tí ẹ dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù

kí n sì máa sùn títí di òru,

tí ń ṣiṣẹ́ àṣekára fún oúnjẹ láti jẹ—

nítorí ó fún àwọn tí ó fẹ́ràn ní oorun.”

Láti rí ìyípadà yìí, a ní láti bẹ̀rẹ̀ nípa ṣíṣàì ní àwọn àfojúsùn tí kò tọ́ fún ìṣàkóso àkókò (tí ó dàbí ẹni pé ó tọ́) àti lílépa àwọn àfojúsùn tó tọ́.

Wò ó, díẹ̀ lára àwọn àfojúsùn tí kò tọ́ tá a lè tètè kó sínú rèé:

  • Ìṣàkóso:Ṣíṣe èrò pé a ti bójú tó àwọn nǹkan, a ò sì nílò ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run
  • Ìdùnnú: Ṣíṣe bí ẹni pé ó dára tó bá ṣeé ṣe
  • Ìmúṣẹ: Títẹjú mọ́ ṣíṣe àwọn nǹkan
  • Jíjé Olùṣàkóso ____: Jíjé fún àwọn ènìyàn ní àfikún láti jèrè iye ara ẹni

Ǹjẹ́ o mọ èyíkéyìí lára àwọn àfojúsùn búburú yìí? Mo mọ̀ pé mo ti kó sínú àwọn ohun tí ayé ń lépa yìí lọ́pọ̀ ìgbà ju bó ṣe yẹ lọ. Àmọ́, ìhìn rere ni pé a lè pa dà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, ká bẹ òun pé kó dárí jì wá, ká sì tún ọkàn wa darí sí ohun tó fẹ́ ká máa ṣe nípa àkókò wa

Ó rọrùn gan-an, sọ pé, "Ọlọ́run, mo kábàámọ̀ fún [ìdí tí kò tọ́]. Jọwọ ran mi lọwọ lati ni oye awọn ibi-afẹde rẹ fun akoko mi ati lati fi igbẹkẹle si ọ ni aarin ti bi mo ṣe lo akoko mi.

Bí Jákọ́bù 4:13-16 (NASB) ṣe kìlọ̀ fún wa, ó ṣe pàtàkì gẹ́gẹ́ bíi Kristẹni láti gbà pé Ọlọ́run ni Olúwa àkókò wa:

Ẹ̀ wá, ẹ̀yin tí ẹ ń sọ pé, "Lónìí tàbí lọ́la, a ó lọ sí ìlú yìí tàbí ìlú yẹn, a ó sì lo ọdún kan níbẹ̀, a ó sì ṣòwò, a ó sì jèrè". Ẹ kò sì mọ ohun tí yóò jẹ́ ìwàláàyè yín lọ́la. Nítorí ìkùukùu lásán ni yín, tí ń farahàn fún ìgbà díẹ̀, tí ó sì ń lọ. Nítorí náà, ohun tí ó yẹ kí ẹ máa sọ ni pé, "Bí Olúwa bá fẹ́, a ó wà láàyè, a ó sì ṣe èyí tàbí èyí". Ṣugbọn nísinsin yìí, ẹ ń ṣògo nínú ìgbéraga yín. Irú ìgbéraga bẹ́ẹ̀ kò dára."

Ẹ jẹ́ kí a gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run, kì í ṣe ara wa, nínú ìṣàkóso àkókò wa lónìí.

 
Ọjọ́ 2

Nípa Ìpèsè yìí

Divine Time Management

Bá a ṣe máa ń lo àkókò wa lọ́nà tó bófin mu lè fa másùnmáwo nígbà tá a bá ń sapá láti "ṣàkóso" ìgbésí ayé wa nípasẹ̀ agbára àti ìkóra-ẹni-níjàánu. Ṣùgbọ́n Bíbélì sọ fún wa pé a máa ń ní àlàáfíà àti ìsinmi nígbà tá a bá g...

More

A fẹ́ láti dúpẹ́ lọ́wọ́ Elizabeth Grace Saunders fún ìpèsè èrò yìí. Fún àlàyé díẹ̀ sii, jọ̀wọ́ ṣàbẹ̀wò: http://www.divinetimebook.com/

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa