Wá Ọlọ́run Láàrin Rẹ̀Àpẹrẹ

Seek God Through It

Ọjọ́ 6 nínú 10

Ó ṣe pàtàkì pé ká máa wá Ọlọ́run. Àmọ́ kó o tó lè wá ẹnì kan tàbí ohun kan, o gbọ́dọ̀ mọ àwọn ànímọ́ rẹ̀. Bákan náà lọ̀rọ̀ rí pẹ̀lú Ọlọ́run. A gbọ́dọ̀ mọ àwọn ànímọ́ Ọlọ́run.

A ò lè kàn mọ irú ẹni tó jẹ́ lọ́nà ṣákálá lórí ohun tá a gbọ́ ní ṣọ́ọ̀ṣì tàbí ohun tá a gbọ́ táwọn èèyàn ń sọ.

Nígbà tí ó bá dá wa lójú, láìsí iyèméjì kankan, pé Ọlọ́run ni Olùpèsè, Olùtùnú, pé Ó bìkítà nípa wa, pé Ó ń rí wa, pé wíwàníhìn-ín Rẹ̀ ni okùn ìgbàlà wa, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, a ó gbé ìgbésẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìṣípayá yẹn. Àmọ́, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa sọ pé òótọ́ ni ohun tí wọ́n gbà gbọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n máa ń ṣàníyàn, tí wọ́n máa ń ní ìsoríkọ́, tí wọ́n sì máa ń ronú pé àwọn ò lè ṣe mọ́. Àmọ́, ó yẹ ká ní ìdánilójú bíi ti pé àwọ̀ ara wa ló dáa jù. Kò sẹ́ni tó lè sọ fún wa pé àwọ̀ wa yàtọ̀ síra, láìka ipò yòówù ká wà sí. Kò sí iyèméjì pé a mọ bí awọ ara wa ṣe rí. A mọ̀, láìsí iyèméjì kankan, pé ọkàn àti ọpọlọ wa ń lù kìkì. Kò sẹ́ni tàbí ohunkóhun tó lè yí wa lérò padà.

Ó yẹ kó dá àwa náà lójú pé Ọlọ́run jẹ́ ẹni tó sọ pé òun jẹ́. Àwọn ìlérí Ọlọ́run ṣì wúlò títí dòní.

Ọjọ́ kẹfà:

  • Máa ṣàṣàrò lórí irú ẹni tí Ọlọ́run jẹ́.
Ọjọ́ 5Ọjọ́ 7

Nípa Ìpèsè yìí

Seek God Through It

Ìrẹ̀wẹ̀sì. Àníyàn. Àwọn okùnfà àti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó ro ni lára máa ń ní ipa tí ó ní agbára lórí ọpọlọ, ìmọ̀lára àtì ìgbé-ayé ẹ̀mí wa. Ní àwọn àkókò yìí, wíwá Ọlọ́run á dàbíi pé ó ṣòro tí kò sì já mọ́ ǹǹkan kan. Èròńgbà ètò kíkà yìí, "Wíwá Ọlọ́run Láàrin Rẹ̀" ni láti gbà ọ́ ní ìyànjú àti láti kọ́ ọ ní ọ̀nà tí o fi lè ṣe ìtara níwájú Ọlọ́run, kí o ba lè ní àlàáfíà Ọlọ́run nínú irú ipòkípò tí o lè wà.

More

A fé dúpẹ́ lọ́wọ́ Brionna Nijah fún ìpèsè ètò yìí. Fún àlàyé díẹ̀ si, Jọ̀wọ́ lọ sí: https://www.brionnanijah.com/