Saamu 118:1-18

Saamu 118:1-18 YCB

Ẹ fi ọpẹ́ fún OLúWA, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé. Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”. Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”. Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù OLúWA wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.” Nínú ìrora mi, mo sọkún sí OLúWA, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀. OLúWA ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi? OLúWA ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé OLúWA ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé OLúWA ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ OLúWA èmi gé wọn kúrò Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ OLúWA èmi gé wọn dànù Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ OLúWA èmi ké wọn dànù. Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n OLúWA ràn mí lọ́wọ́. OLúWA ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi. Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún OLúWA ń ṣe ohun agbára! Ọwọ́ ọ̀tún OLúWA ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún OLúWA ń ṣe ohun agbára!” Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí OLúWA ṣe. OLúWA bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.