Ẹkun Jeremiah 5:15-22

Ẹkun Jeremiah 5:15-22 YCB

Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa. Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀. Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú. Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri. Ìwọ, OLúWA, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn. Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́? Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, OLúWA, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì Àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.