ORIN DAFIDI 41

41
Adura Ẹni tí ń Ṣàìsàn
1Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ń ro ti àwọn aláìní:
OLUWA yóo gbà á ní ọjọ́ ìpọ́njú.
2OLUWA yóo máa ṣọ́ ọ, yóo sì dá a sí.
Yóo ní ayọ̀ ní ilẹ̀ náà;
OLUWA kò ní fi í lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
3Nígbà tí ó bá wà ní ìdùbúlẹ̀ àìsàn,
OLUWA yóo fún un lókun;
ní àkókò àìlera OLUWA yóo wo gbogbo àrùn rẹ̀ sàn.
4Mo ní, “OLUWA, ṣàánú mi kí o sì wò mí sàn;
mo ti ṣẹ̀ ọ́.”
5Àwọn ọ̀tá mi ń ro ibi sí mi, wọ́n ń wí pé,
“Nígbà wo ni yóo kú, tí orúkọ rẹ̀ yóo parẹ́?”
6Tí ọ̀kan bá wá bẹ̀ mí wò,
ọ̀rọ̀ tí kò lórí, tí kò nídìí
ni yóo máa sọ;
bẹ́ẹ̀ ni ninu ọkàn rẹ̀, èrò ibi ni yóo máa gbà.
Nígbà tí ó bá jáde,
yóo máa rò mí kiri.
7Gbogbo àwọn tí ó kórìíra mi
jọ ń sọ̀rọ̀ wújẹ́wújẹ́ nípa mi;
ohun tó burú jùlọ ni wọ́n ń rò sí mi.
8Wọ́n ń wí pé, “Àìsàn burúkú ti gbé e dálẹ̀;
kò ní dìde mọ́ níbi tí ó dùbúlẹ̀ sí.”
9Àní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi tí mo gbẹ́kẹ̀lé,
tí ó ń jẹun nílé mi,
ó ti kẹ̀yìn sí mí.#Mat 26:23; Mak 14:18; Luk 22:21; Joh 13:18
10Ṣugbọn, OLUWA, ṣàánú mi;
gbé mi dìde, kí n lè san ẹ̀san fún un.
11Kí n lè mọ̀ pé o fẹ́ràn mi,
nígbà tí ọ̀tá kò bá borí mi.
12O ti gbé mi ró nítorí ìwà pípé mi,
o sì fi ẹsẹ̀ mi múlẹ̀ níwájú rẹ títí lae.
13Ìyìn ni fún OLUWA, Ọlọrun Israẹli,
lae ati laelae.
Amin! Amin!#O. Daf 106:48
ÌWÉ ORIN KEJI
(Orin Dafidi 42–72)

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 41: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa