ORIN DAFIDI 16

16
Mo Sá di OLUWA
1Pa mí mọ́ Ọlọrun, nítorí ìwọ ni mo sá di.
2Mo wí fún ọ, OLUWA, pé, “Ìwọ ni Oluwa mi;
ìwọ nìkan ni orísun ire mi.”
3Nípa àwọn eniyan mímọ́ tí ó wà nílẹ̀ yìí,
wọ́n jẹ́ ọlọ́lá tí àwọn eniyan fẹ́ràn.#16:3 Ìtumọ̀ ẹsẹ kẹta yìí kò yéni ninu Bibeli èdè Heberu.
4“Ìbànújẹ́ àwọn tí ń sá tọ ọlọrun mìíràn lẹ́yìn yóo pọ̀:
Èmi kò ní bá wọn ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ fún ìrúbọ,
bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kò ní gbọ́ orúkọ wọn lẹ́nu mi.”
5OLUWA, ìwọ ni ìpín mi, ìwọ ni mo yàn;
ìwọ ni ò ń jẹ́ kí ọ̀ràn mi fìdí múlẹ̀.
6Ìpín tí ó bọ́ sí mi lọ́wọ́ dára pupọ;
ogún rere ni ogún ti mo jẹ.
7Èmi óo máa yin OLUWA, ẹni tí ó ń fún mi ní òye;
ọkàn mi ó sì máa tọ́ mi sọ́nà ní òròòru.
8Mò ń wo OLUWA ní iwájú mi nígbà gbogbo,
nítorí pé Ọlọrun dúró tì mí, ẹsẹ̀ mi kò ní yẹ̀.
9Nítorí náà ni ọkàn mi ṣe ń yọ̀, tí inú mi dùn;
ara sì rọ̀ mí.
10Nítorí o kò ní gbàgbé mi sí ipò òkú,
bẹ́ẹ̀ ni o kò ní jẹ́ kí ẹni tí ó fi tọkàntọkàn sìn ọ́ rí ìdíbàjẹ́.#A. Apo 13:35
11O ti fi ọ̀nà ìyè hàn mí;
ayọ̀ kíkún ń bẹ ní iwájú rẹ,
ìgbádùn àìlópin sì ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.#A. Apo 2:25-28

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 16: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa