ORIN DAFIDI 17

17
Adura fún Ìdáláre
1Gbọ́ tèmi OLUWA, àre ni ẹjọ́ mi;#17:1 Àwọn Bibeli mìíràn kà báyìí pé: “Gbọ́ tèmi, OLUWA, olódodo ni mí.”
fi ìtara gbọ́ igbe mi.
Fetí sí adura mi nítorí kò sí ẹ̀tàn ní ẹnu mi.
2Jẹ́ kí ìdáláre mi ti ọ̀dọ̀ rẹ wá;
kí o sì rí i pé ẹjọ́ mi tọ́.
3Yẹ ọkàn mi wò; bẹ̀ mí wò lóru.
Dán mi wò, o kò ní rí ohun burúkú kan;
n kò ní fi ẹnu mi dẹ́ṣẹ̀.
4Nítorí ohun tí o wí nípa èrè iṣẹ́ ọwọ́ eniyan,
mo ti yàgò fún àwọn oníwà ipá.
5Mò ń tọ ọ̀nà rẹ tààrà;
ẹsẹ̀ mi kò sì yọ̀.
6Mo ké pè ọ́, dájúdájú ìwọ Ọlọrun yóo dá mi lóhùn,
dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
7Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn lọ́nà ìyanu,
fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ
kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó gbógun tì wọ́n.
8Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú,
dáàbò bò mí lábẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ;
9lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú tí ó gbé ìjà kò mí,
àní lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.
10Ojú àánú wọn ti fọ́,
ọ̀rọ̀ ìgbéraga sì ń ti ẹnu wọn jáde.
11Wọn ń lépa mi; wọ́n sì ti yí mi ká báyìí;
wọn ń ṣọ́ bí wọn ó ṣe bì mí ṣubú.
12Wọ́n dàbí kinniun tí ó ṣetán láti pa ẹran jẹ,
àní bí ọmọ kinniun tí ó ba ní ibùba.
13Dìde, OLUWA! Dojú kọ wọ́n; là wọ́n mọ́lẹ̀;
fi idà rẹ gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.
14OLUWA, fi ọwọ́ ara rẹ gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan wọnyi;
àwọn tí ìpín wọn jẹ́ ohun ti ayé yìí,
fi ohun rere jíǹkí àwọn ẹni tí o pamọ́;
jẹ́ kí àwọn ọmọ jẹ àjẹyó;
sì jẹ́ kí àwọn ọmọ ọmọ wọn rí ogún wọn jẹ.#17:14 Ìtumọ̀ ẹsẹ kẹrinla kò yéni yékéyéké ninu Bibeli èdè Heberu .
15Ní tèmi, èmi óo rí ojú rẹ nítorí òdodo mi,
ìrísí rẹ yóo sì tẹ́ mi lọ́rùn nígbà tí mo bá jí.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 17: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa