Ó wó àgọ́ rẹ̀ lulẹ̀, bí ìgbà tí eniyan wó ahéré oko. Ó pa gbogbo ibi tí wọ́n ti ń ṣe àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀ run. OLUWA ti fi òpin sí àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀, ati ọjọ́ ìsinmi ní Sioni. Ó sì ti fi ibinu gbígbóná rẹ̀, kọ ọba ati alufaa sílẹ̀. OLUWA kò bìkítà fún pẹpẹ rẹ̀ mọ́, ó sì ti kọ ibi mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Ó ti fi odi ààfin rẹ̀ lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́; wọ́n pariwo ńlá ninu ilé OLUWA gẹ́gẹ́ bíi ti ọjọ́ àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀. OLUWA ti pinnu láti wó odi Sioni lulẹ̀. Ó fi okùn ìwọ̀n wọ̀n ọ́n, kò sì rowọ́ láti parun. Ó jẹ́ kí ilé ìṣọ́ ati odi ìlú wó lulẹ̀ pẹlu ìbànújẹ́, wọ́n sì di àlàpà papọ̀. Àwọn ẹnubodè rẹ̀ ti rì, wọ́n ti wọlẹ̀; ó ti ṣẹ́ àwọn ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn bodè; ọba rẹ̀ ati àwọn olórí rẹ̀ wà láàrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn; òfin kò sí mọ́, àwọn wolii rẹ̀ kò sì ríran láti ọ̀dọ̀ OLUWA mọ́. Àwọn àgbààgbà Sioni jókòó lórí ilẹ̀, wọ́n dákẹ́ rọ́rọ́, wọ́n ku eruku sórí, wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀. Àwọn ọmọbinrin Jerusalẹmu doríkodò.
Kà ẸKÚN JEREMAYA 2
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ẸKÚN JEREMAYA 2:6-10
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò