JOBU 26:7-14

JOBU 26:7-14 YCE

Ó na ìhà àríwá sórí òfuurufú, ó sì so ayé rọ̀ sí òfuurufú. Ó di omi papọ̀ ninu ìkùukùu rẹ̀ tí ó nípọn, sibẹ ìkùukùu kò fà ya. Ó dí ojú òṣùpá, ó sì fi ìkùukùu bò ó. Ó ṣe òbìrìkítí kan sórí omi, ó fi ṣe ààlà láàrin òkùnkùn ati ìmọ́lẹ̀. Àwọn òpó ọ̀run mì tìtì, wọ́n sì wárìrì nítorí ìbáwí rẹ̀. Nípa agbára rẹ̀, ó mú kí òkun parọ́rọ́, nípa ìmọ̀ rẹ̀, ó pa Rahabu. Ó fi afẹ́fẹ́ ṣe ojú ọ̀run lọ́ṣọ̀ọ́; ọwọ́ ló fi pa ejò tí ń fò. Ṣugbọn kékeré nìyí ninu agbára rẹ̀, díẹ̀ ni a tíì gbọ́ nípa iṣẹ́ rẹ̀! Nítorí náà ta ló lè mọ títóbi agbára rẹ̀?”