O. Daf 56:1-13
O. Daf 56:1-13 Bibeli Mimọ (YBCV)
ỌLỌRUN, ṣãnu fun mi: nitoriti enia nfẹ gbe mi mì; o mba mi jà lojojumọ, o nni mi lara. Awọn ọta mi nfẹ igbe mi mì lojojumọ: nitori awọn ti nfi igberaga ba mi ja pọ̀. Nigbati ẹ̀ru ba mbà mi, emi o gbẹkẹle ọ. Nipa Ọlọrun li emi o ma yìn ọ̀rọ rẹ̀, Ọlọrun li emi o gbẹkẹ mi le, emi kì yio bèru: kili ẹran-ara le ṣe si mi. Lojojumọ ni nwọn nlọ́ ọ̀rọ mi: ibi ni gbogbo ìro inu wọn si mi: Nwọn kó ara wọn jọ, nwọn ba, nwọn kiyesi ìrin mi, nwọn ti nṣọ̀na ọkàn mi. Nwọn ha le ti ipa aiṣedede là? ni ibinu, bi awọn enia na lulẹ̀, Ọlọrun. Iwọ nka ìrìnkiri mi: fi omije mi sinu igo rẹ: nwọn ko ha si ninu iwe rẹ bi? Li ọjọ ti mo ba kigbe, nigbana li awọn ọta mi yio pẹhinda: eyi li emi mọ̀: nitoripe Ọlọrun wà fun mi. Nipa Ọlọrun li emi o ma yìn ọ̀rọ rẹ̀: nipa Oluwa li emi o ma yìn ọ̀rọ rẹ̀. Ọlọrun li emi gbẹkẹ mi le, emi kì yio bẹ̀ru kili enia le ṣe si mi. Ẹjẹ́ rẹ mbẹ lara mi, Ọlọrun: emi o fi iyìn fun ọ. Nitoripe iwọ li o ti gbà ọkàn mi lọwọ ikú: iwọ ki yio ha gbà ẹsẹ mi lọwọ iṣubu? ki emi ki o le ma rìn niwaju Ọlọrun ni imọlẹ awọn alãye?
O. Daf 56:1-13 Yoruba Bible (YCE)
Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí pé àwọn eniyan ń lépa mi; ọ̀tá gbógun tì mí tọ̀sán-tòru. Àwọn ọ̀tá ń lépa mi tọ̀sán-tòru, ọpọlọpọ ní ń bá mi jà tìgbéraga-tìgbéraga. Nígbà tí ẹ̀rù bá ń bà mí, èmi yóo gbẹ́kẹ̀lé ọ. Ọlọrun, mo yìn ọ́ fún ọ̀rọ̀ rẹ, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù; kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe? Tọ̀sán-tòru ni wọ́n ń da ọ̀rọ̀ mi rú; ibi ni gbogbo èrò tí wọn ń gbà sí mi. Wọ́n kó ara wọn jọ, wọ́n sápamọ́, wọ́n ń ṣọ́ ìrìn ẹsẹ̀ mi, bí wọn ṣé ń dọdẹ ẹ̀mí mi. Nítorí náà, san ẹ̀san ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn; ninu ibinu rẹ, Ọlọrun, ré àwọn eniyan yìí lulẹ̀. O sá mọ gbogbo ìdààmú mi; ati bí omijé mi ti pọ̀ tó, wọ́n ṣá wà ní àkọsílẹ̀ ninu ìwé rẹ. A óo lé àwọn ọ̀tá mi pada ní ọjọ́ tí mo bá ké pè ọ́. Mo mọ̀ dájú pé Ọlọrun ń bẹ fún mi. Ọlọrun, tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀, OLUWA, tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀; Ọlọrun ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù. Kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe? Èmi óo san ẹ̀jẹ́ mi fún ọ, Ọlọrun; n óo sì mú ẹbọ ọpẹ́ wá fún ọ. Nítorí pé o ti gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ ikú, o gbà mí, o kò jẹ́ kí n kọsẹ̀, kí n lè máa rìn níwájú Ọlọrun ninu ìmọ́lẹ̀ ìyè.
O. Daf 56:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi; ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà sí mi, wọn ń ni mi lára. Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́, àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn. Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí, èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ. Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ, nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi? Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́, wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi. Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi. San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn; Ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀. Kọ ẹkún mi sílẹ̀; kó omijé mi sí ìgò rẹ, wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí? Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́ nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi. Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú OLúWA, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀: Nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi: ẹ̀rù kì yóò bà mí. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi? Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run: èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ. Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú, kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.