O. Daf 148:1-14
O. Daf 148:1-14 Bibeli Mimọ (YBCV)
Ẹ fi iyìn fun Oluwa, Ẹ fi iyìn fun Oluwa lati ọrun wá; ẹ fi iyìn fun u ni ibi giga. Ẹ fi iyìn fun u, gbogbo ẹnyin angeli rẹ̀; ẹ fi iyìn fun u, gbogbo ẹnyin ọmọ-ogun rẹ̀. Ẹ fi iyìn fun u, õrun ati oṣupa; ẹ fi iyìn fun u, gbogbo ẹnyin irawọ imọlẹ. Ẹ fi iyìn fun u, ẹnyin ọrun awọn ọrun, ati ẹnyin omi ti mbẹ loke ọrun. Jẹ ki nwọn ki o ma yìn orukọ Oluwa; nitori ti on paṣẹ, a si da wọn. O si fi idi wọn mulẹ lai ati lailai; o si ti ṣe ilana kan ti kì yio kọja. Ẹ yìn Oluwa lati aiye wá, ẹnyin erinmi, ati gbogbo ibu-omi; Iná ati yinyin òjo-didì ati ikũku; ìji mu ọ̀rọ rẹ̀ ṣẹ; Ẹnyin òke nla, ati gbogbo òke kekere; igi eleso, ati gbogbo igi Kedari; Ẹranko, ati gbogbo ẹran-ọ̀sin; ohun ti nrakò, ati ẹiyẹ́ ti nfò; Awọn ọba aiye, ati gbogbo enia; ọmọ-alade, ati gbogbo onidajọ aiye; Awọn ọdọmọkunrin ati awọn wundia, awọn arugbo enia ati awọn ọmọde; Ki nwọn ki o ma yìn orukọ Oluwa; nitori orukọ rẹ̀ nikan li o li ọlá; ogo rẹ̀ bori aiye on ọrun. O si gbé iwo kan soke fun awọn enia rẹ̀, iyìn fun gbogbo enia mimọ́ rẹ̀; ani awọn ọmọ Israeli, awọn enia ti o sunmọ ọdọ rẹ̀. Ẹ fi iyìn fun Oluwa.
O. Daf 148:1-14 Yoruba Bible (YCE)
Ẹ yin OLUWA! Ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ yìn ín lókè ọ̀run. Ẹ yìn ín, gbogbo ẹ̀yin angẹli rẹ̀; ẹ yìn ín, gbogbo ẹ̀yin ọmọ ogun rẹ̀. Ẹ yìn ín, oòrùn ati òṣùpá; ẹ yìn ín, gbogbo ẹ̀yin ìràwọ̀ tí ń tàn. Ẹ yìn ín, ọ̀run tí ó ga jùlọ; yìn ín, omi tí ó wà lójú ọ̀run. Ẹ jẹ́ kí wọ́n máa yin orúkọ OLUWA, nítorí nípa àṣẹ rẹ̀ ni a fi dá wọn. Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ títí laelae; ó sì pààlà fún wọn tí wọn kò gbọdọ̀ ré kọjá. Ẹ yin OLUWA, ẹ̀yin ẹ̀dá ayé, ẹ̀yin erinmi ńláńlá inú òkun ati gbogbo ibú omi; iná ati yìnyín, ati ìrì dídì, ati ẹ̀fúùfù líle tí ń mú àṣẹ rẹ̀ ṣẹ. Ẹ yìn ín, ẹ̀yin òkè ńláńlá ati òkè kéékèèké, ẹ̀yin igi eléso ati igi kedari; ẹ̀yin ẹranko ìgbẹ́ ati ẹran ọ̀sìn, ẹ̀yin ẹ̀dá tí ń fàyà fà ati ẹyẹ tí ń fò. Ẹ yìn ín, ẹ̀yin ọba ayé ati gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹ̀yin ìjòyè ati gbogbo onídàájọ́ ayé; ẹ̀yin ọdọmọkunrin ati ọlọ́mọge, ẹ̀yin ọmọde ati ẹ̀yin àgbààgbà. Ẹ jẹ́ kí wọn yin orúkọ OLUWA, nítorí pé orúkọ rẹ̀ nìkan ni ó ga jù; ògo rẹ̀ sì ga ju ayé ati ọ̀run lọ. Ó ti fún àwọn eniyan rẹ̀ ní agbára, ó sì fún àwọn eniyan rẹ̀ mímọ́ ní ìyìn; ó fún àwọn eniyan Israẹli, tí ó wà lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ̀.
O. Daf 148:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ẹ fi ìyìn fún OLúWA. Ẹ fi ìyìn fún OLúWA láti ọ̀run wá, Ẹ fi ìyìn fún un níbi gíga. Ẹ fi ìyìn fún un, gbogbo ẹ̀yin angẹli rẹ̀ Ẹ fi ìyìn fún un, gbogbo ẹ̀yin ọmọ-ogun rẹ̀ Ẹ fi ìyìn fún un, oòrùn àti òṣùpá Ẹ fi ìyìn fún un, gbogbo ẹ̀yin ìràwọ̀ ìmọ́lẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún un, ẹ̀yin ọ̀run àti àwọn ọ̀run gíga àti ẹ̀yin omi tí ń bẹ ní òkè ọ̀run. Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ OLúWA nítorí ó pàṣẹ a sì dá wọn Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láé àti láéláé ó sì ti ṣe ìlànà kan tí kì yóò já. Ẹ yin OLúWA láti ilẹ̀ ayé wá ẹ̀yin ẹ̀dá inú Òkun títóbi àti ẹ̀yin ibú Òkun Mọ̀nàmọ́ná àti òjò yìnyín ìdí omi àti àwọn ìkùùkuu, ìjì líle tí ń mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; Òkè ńlá àti gbogbo òkè kéékèèkéé, igi eléso àti gbogbo igi kedari, Àwọn ẹranko ńlá àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ohun afàyàfà àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́: Àwọn ọba ayé àti ènìyàn ayé gbogbo àwọn ọmọ-aládé àti gbogbo àwọn onídàájọ́ ayé, Ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin àwọn arúgbó àti àwọn ọmọdé. Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ OLúWA nítorí orúkọ rẹ̀ nìkan ni ó ní ọlá ògo rẹ̀ kọjá ayé àti ọ̀run Ó sì gbé ìwo kan sókè fún àwọn ènìyàn rẹ̀, ìyìn fún gbogbo ènìyàn mímọ́ rẹ̀ àní fún àwọn ọmọ Israẹli, àwọn ènìyàn tí ó súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.