Isaiah 44:21-23

Isaiah 44:21-23 YCB

“Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ. Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.” Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí OLúWA ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí OLúWA ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.