II. Sam 13

13
Amnoni ati Tamari
1O si ṣe, lẹhin eyi, Absalomu ọmọ Dafidi ni aburo obinrin kan ti o ṣe arẹwà, orukọ rẹ̀ a si ma jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi si fẹràn rẹ̀.
2Amnoni si banujẹ titi o fi ṣe aisan nitori Tamari aburo rẹ̀ obinrin; nitoripe wundia ni; o si ṣe ohun ti o ṣoro li oju Amnoni lati ba a ṣe nkan kan.
3Ṣugbọn Amnoni ni ọrẹ́ kan, orukọ rẹ̀ a si ma jẹ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹgbọ́n Dafidi: Jonadabu si jẹ alarekereke enia gidigidi.
4O si wi fun u pe, ẽṣe ti iwọ ọmọ ọba nfi nrù lojojumọ bayi? o kì yio ha sọ fun mi? Amnoni si wi fun u pe, emi fẹ Tamari aburo Absalomu arakunrin mi.
5Jonadabu si wi fun u pe, dubulẹ ni ibusùn rẹ ki iwọ ki o si ṣe bi ẹnipe ara rẹ kò yá: baba rẹ yio si wá iwò ọ, iwọ o si wi fun u pe, Jọ̀wọ jẹ ki Tamari aburo mi ki o wá ki o si fun mi li onjẹ ki o si se onjẹ na niwaju mi ki emi ki o ri i, emi o si jẹ ẹ li ọwọ́ rẹ̀.
6Amnoni si dubulẹ, o si ṣe bi ẹnipe on ṣaisan: ọba si wá iwò o, Amnoni si wi fun ọba pe, Jọwọ, jẹ ki Tamari aburo mi ki o wá, ki o si din akarà meji li oju mi, emi o si jẹ li ọwọ́ rẹ̀.
7Dafidi si ranṣẹ si Tamari ni ile pe, Lọ si ile Amnoni ẹgbọ́n rẹ, ki o si ṣe ti onjẹ fun u.
8Tamari si lọ si ile Amnoni ẹgbọ́n rẹ̀, on si mbẹ ni ibulẹ. Tamari si mu iyẹfun, o si pò o, o si fi ṣe akara li oju rẹ̀, o si din akara na.
9On si mu awo na, o si dà a sinu awo miran niwaju rẹ̀; ṣugbọn o kọ̀ lati jẹ. Amnoni si wipe, jẹ ki gbogbo ọkunrin jade kuro lọdọ mi. Nwọn si jade olukuluku ọkunrin kuro lọdọ rẹ̀.
10Amnoni si wi fun Tamari pe, mu onjẹ na wá si yara, emi o si jẹ lọwọ rẹ. Tamari si mu akara ti o ṣe, o si mu u tọ̀ Amnoni ẹgbọ́n rẹ̀ ni iyẹwu.
11Nigbati o si sunmọ ọ lati fi onjẹ fun u, on si di i mu, o si wi fun u pe, wá dubulẹ tì mi, aburo mi.
12On si da a lohùn wipe, Bẹ̃kọ ẹgbọ́n mi, máṣe tẹ́ mi; nitoripe ko tọ́ ki a ṣe iru nkan bẹ̃ ni Israeli, iwọ máṣe huwa were yi.
13Ati emi, nibo li emi o gbe itiju mi wọ̀? iwọ o si dabi ọkan ninu awọn aṣiwere ni Israeli. Njẹ nitorina, emi bẹ̀ ọ, sọ fun ọba; nitoripe on kì yio kọ̀ lati fi mi fun ọ.
14Ṣugbọn o kọ̀ lati gbọ́ ohùn rẹ̀; o si fi agbara mu u, o si ṣẹgun rẹ̀, o si ba a dapọ̀.
15Amnoni si korira rẹ̀ gidigidi, irira na si wá jù ifẹ ti on ti ni si i ri lọ. Amnoni si wi fun u pe, Dide, ki o si ma lọ.
16On si wi fun u pe, Ko ha ni idi bi; lilé ti iwọ nlé mi yi buru jù eyi ti iwọ ti ṣe si mi lọ. Ṣugbọn on ko fẹ gbọ́ tirẹ̀.
17On si pe ọmọ-ọdọ rẹ̀ ti iṣe iranṣẹ rẹ̀, o si wi fun u pe, Jọwọ, tì obinrin yi sode fun mi, ki o si ti ilẹkùn mọ ọ.
18On si ni aṣọ alaràbara kan li ara rẹ̀: nitori iru aṣọ awọ̀leke bẹ̃ li awọn ọmọbinrin ọba ti iṣe wundia ima wọ̀. Iranṣẹ rẹ̀ si mu u jade, o si ti ilẹkun mọ ọ.
19Tamari si bu ẽru si ori rẹ̀, o si fa aṣọ alaràbara ti mbẹ lara rẹ̀ ya, o si ka ọwọ́ rẹ̀ le ori, o si nkigbe bi o ti nlọ.
20Absalomu ẹgbọ́n rẹ̀ si bi i lere pe, Amnoni ẹgbọ́n rẹ ba ọ ṣe bi? njẹ aburo mi, dakẹ; ẹgbọ́n rẹ ni iṣe; má fi nkan yi si ọkàn rẹ. Tamari si joko ni ibanujẹ ni ile Absalomu ẹgbọ́n rẹ̀.
21Ṣugbọn nigbati Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nkan wọnyi, inu rẹ̀ bajẹ gidigidi.
22Absalomu ko si ba Amnoni sọ nkan, rere, tabi buburu: nitoripe Absalomu korira Amnoni nitori eyi ti o ṣe, ani ti o fi agbara mu Tamari aburo rẹ̀.
Absalomu Gbẹ̀san
23O si ṣe, lẹhin ọdun meji, Absalomu si ni olurẹrun agutan ni Baal-hasori, eyiti o gbè Efraimu: Absalomu si pe gbogbo awọn ọmọ ọba.
24Absalomu si tọ̀ ọba wá, o si wipe, Wõ, jọwọ, iranṣẹ rẹ ni olurẹrun agutan, emi bẹ̀ ọ, jẹ ki ọba, ati awọn iranṣẹ rẹ̀ ba iranṣẹ rẹ lọ.
25Ọba si wi fun Absalomu pe, Bẹ̃kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ, má jẹ ki gbogbo wa lọ, ki a má mu ọ nawo pupọ. O si rọ̀ ọ gidigidi, ṣugbọn on kò fẹ lọ, o si sure fun u.
26Absalomu si wi pe, Bi kò ba le ri bẹ̃, emi bẹ̀ ọ, jẹ ki Amnoni ẹgbọ́n mi ba wa lọ. Ọba si wipe, Idi rẹ̀ ti yio fi ba ọ lọ?
27Absalomu si rọ̀ ọ, on si jẹ ki Amnoni ati gbogbo awọn ọmọ ọba ba a lọ.
28Absalomu si fi aṣẹ fun awọn iranṣẹ rẹ̀ pe, Ki ẹnyin ki o ma kiyesi akoko ti ọti-waini yio mu ọkàn Amnoni dùn, emi o si wi fun nyin pe, Kọlu Amnoni; ki ẹ si pa a: ẹ má bẹ̀ru: ṣe emi li o fi aṣẹ fun nyin? ẹ ṣe giri, ki ẹ ṣe bi alagbara ọmọ.
29Awọn iranṣẹ Absalomu si ṣe si Amnoni gẹgẹ bi Absalomu ti paṣẹ. Gbogbo awọn ọmọ ọba si dide, olukuluku gun ibaka rẹ̀, nwọn si sa.
30O si ṣe, nigbati nwọn mbẹ li ọ̀na, ihìn si de ọdọ Dafidi pe, Absalomu pa gbogbo awọn ọmọ ọba, ọkan kò si kù ninu wọn.
31Ọba si dide, o si fa aṣọ rẹ̀ ya, o si dubulẹ ni ilẹ; gbogbo awọn iranṣẹ rẹ̀ ti nwọn duro tì i si fa aṣọ wọn ya.
32Jonadabu ọmọ Ṣimea arakonrin Dafidi si dahùn o si wipe, Ki oluwa mi ọba ki o máṣe rò pe nwọn ti pa gbogbo awọn ọdọmọde-kọnrin awọn ọmọ ọba; nitoripe Amnoni nikanṣoṣo li o kú: nitori lati ẹnu Absalomu wá li a ti pinnu rẹ̀ lati ọjọ ti o ti fi agbara mu Tamari aburo rẹ̀.
33Njẹ ki oluwa mi ọba ki o máṣe fi nkan yi si ọkàn pe, gbogbo awọn ọmọ ọba li o kú: nitori Amnoni nikanṣoṣo li o kú.
34Absalomu si sa. Ọdọmọkunrin na ti nṣọ̀na si gbe oju rẹ̀ soke, o si ri pe, ọ̀pọ enia mbọ̀ li ọ̀na lẹhin rẹ̀ lati iha oko wá.
35Jonadabu si wi fun ọba pe, Wõ, awọn ọmọ ọba mbọ̀: gẹgẹ bi ọ̀rọ iranṣẹ rẹ, bẹ̃ li o ri.
36O si ṣe, nigbati o ti pari ọ̀rọ isọ, si wõ, awọn ọmọ ọba de, nwọn si gbe ohùn wọn soke, nwọn si sọkun: ọba ati gbogbo awọn iranṣẹ rẹ̀ pẹlu si sọkun nlanla.
37Absalomu si sa, o si tọ̀ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi si nkãnu nitori ọmọ rẹ̀ lojojumọ.
38Absalomu si sa, o si lọ si Geṣuri, o si gbe ibẹ li ọdun mẹta.
39Ọkàn Dafidi ọba si fà gidigidi si Absalomu: nitoriti o ti gbà ipẹ̀ niti Amnoni: o sa ti kú.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

II. Sam 13: YBCV

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀