ORIN DAFIDI 92

92
Orin Ìyìn
1Ó dára kí eniyan máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, OLUWA;
kí ó sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ, ìwọ Ọ̀gá Ògo;
2ó dára kí eniyan máa kéde ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ní òwúrọ̀,
kí ó máa kéde òtítọ́ rẹ ní alẹ́,
3pẹlu orin, lórí ohun èlò orin olókùn mẹ́wàá,
ati hapu.
4Nítorí ìwọ, OLUWA, ti mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ;
OLUWA, mò ń fi ayọ̀ kọrin nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ tóbi pupọ, OLÚWA!
Èrò rẹ sì jinlẹ̀ pupọ!
6Òpè eniyan kò lè mọ̀,
kò sì le yé òmùgọ̀:#Ọgb 13:1
7pé bí eniyan burúkú bá tilẹ̀ rú bíi koríko,
tí gbogbo àwọn aṣebi sì ń gbilẹ̀,
ó dájú pé ìparun ayérayé ni òpin wọn.
8Ṣugbọn ẹni àgbéga títí lae ni ọ́, OLUWA.
9Wò ó, OLUWA, àwọn ọ̀tá rẹ yóo parun;
gbogbo àwọn aṣebi yóo sì fọ́n ká.
10Ṣugbọn o ti gbé mi ga, o ti fún mi lágbára bíi ti ẹfọ̀n;
o ti da òróró dáradára sí mi lórí.
11Mo ti fi ojú mi rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi,
mo sì ti fi etí mi gbọ́ ìparun àwọn ẹni ibi tí ó gbé ìjà kò mí.
12Àwọn olódodo yóo gbilẹ̀ bí igi ọ̀pẹ,
wọn óo dàgbà bí igi kedari ti Lẹbanoni.
13Wọ́n dàbí igi tí a gbìn sí ilé OLUWA,
tí ó sì ń dàgbà ninu àgbàlá Ọlọrun wa.
14Wọn á máa so èso títí di ọjọ́ ogbó wọn,
wọn á máa lómi lára, ewé wọn á sì máa tutù nígbà gbogbo;
15láti fihàn pé olóòótọ́ ni OLUWA;
òun ni àpáta mi, kò sì sí aiṣododo lọ́wọ́ rẹ̀.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 92: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa