Kí Ọlọrun óo ṣàánú wa, kí ó bukun wa; kí ojú rẹ̀ tan ìmọ́lẹ̀ sí wa lára; kí gbogbo ayé lè mọ ọ̀nà rẹ̀; kí gbogbo orílẹ̀-èdè sì mọ ìgbàlà rẹ̀. Jẹ́ kí àwọn eniyan ó máa yìn ọ́, Ọlọrun; jẹ́ kí gbogbo eniyan máa yìn ọ́! Kí inú àwọn orílẹ̀-èdè ó dùn, kí wọn ó máa kọrin ayọ̀, nítorí pé ò ń ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan láìṣe ojuṣaaju; o sì ń tọ́ gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ayé. Jẹ́ kí àwọn eniyan ó máa yìn ọ́, Ọlọrun; jẹ́ kí gbogbo eniyan máa yìn ọ́! Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀ ìkórè jáde; Ọlọrun, àní Ọlọrun wa, bukun wa. Ọlọrun bukun wa, kí gbogbo ayé máa bẹ̀rù rẹ̀.
Kà ORIN DAFIDI 67
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 67:1-7
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò