Ìwọ alágbára, kí ló dé tí o fi ń fọ́nnu, kí ló dé tí ò ń fọ́nnu tọ̀sán-tòru? Ẹni ìtìjú ni ọ́ lójú Ọlọrun. Ò ń pète ìparun; ẹnu rẹ dàbí abẹ tí ó mú, ìwọ alárèékérekè. O fẹ́ràn ibi ju ire lọ, o sì fẹ́ràn irọ́ ju òtítọ́ lọ. O fẹ́ràn gbogbo ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́, Ìwọ ẹlẹ́tàn! Nítòótọ́ Ọlọrun óo bá ọ kanlẹ̀, yóo gbá ọ mú, yóo sì fà ọ́ já kúrò ninu ilé rẹ; yóo fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. Nígbà tí àwọn olódodo bá rí i, ẹ̀rù óo bà wọ́n, wọn óo fi rẹ́rìn-ín, wọn óo sì wí pé, “Wo ẹni tí ó kọ̀, tí kò fi Ọlọrun ṣe ààbò rẹ̀, ṣugbọn ó gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀, ati jamba tí ó ń ta fún ẹlòmíràn.” Ṣugbọn èmi dàbí igi olifi tútù tí ń dàgbà ninu ilé OLUWA, mo gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọrun tí kì í yẹ̀, lae ati laelae. N óo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ títí lae, nítorí ohun tí o ṣe, n óo máa kéde orúkọ rẹ níwájú àwọn olùfọkànsìn rẹ, nítorí pé ó dára bẹ́ẹ̀.
Kà ORIN DAFIDI 52
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 52:1-9
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò