ORIN DAFIDI 33

33
Orin Ìyìn
1Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA, ẹ̀yin olódodo!
Yíyin OLUWA ni ó yẹ ẹ̀yin olóòótọ́.
2Ẹ fi gòjé yin OLUWA,
ẹ fi hapu olókùn mẹ́wàá kọ orin sí i.
3Ẹ kọ orin titun sí i,
ẹ fi ohun èlò ìkọrin olókùn dárà,
kí ẹ sì hó ìhó ayọ̀.
4Nítorí ọ̀rọ̀ OLUWA dúró ṣinṣin;
òtítọ́ sì ni ó fi ń ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.
5OLUWA fẹ́ràn òdodo ati ẹ̀tọ́;
ayé kún fún ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
6Ọ̀rọ̀ ni OLUWA fi dá ojú ọ̀run,
èémí ẹnu rẹ̀ ni ó sì fi dá oòrùn, òṣùpá, ati àwọn ìràwọ̀.
7Ó wọ́ gbogbo omi òkun jọ bí òkìtì;
ó pa gbogbo omi inú àwọn ibú pọ̀ bí ẹni pé ó rọ ọ́ sinu àgbá ńlá.
8Kí gbogbo ayé bẹ̀rù OLUWA,
kí gbogbo aráyé dúró níwájú rẹ̀ pẹlu ọ̀wọ̀ ati ìbẹ̀rù!
9Nítorí pé OLUWA sọ̀rọ̀, ayé wà;
ó pàṣẹ, ayé sì dúró.
10OLUWA sọ ìmọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè di asán;
ó sì mú kí ètò àwọn eniyan já sófo.
11Ètò OLUWA wà títí lae,
èrò ọkàn rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.
12Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn,
àní àwọn eniyan tí ó yàn gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀!
13OLUWA bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run,
ó rí gbogbo eniyan;
14láti orí ìtẹ́ rẹ̀ tí ó gúnwà sí,
ó wo gbogbo aráyé.
15Òun ni ó dá ọkàn gbogbo wọn,
tí ó sì ń mójútó gbogbo ìṣe wọn.
16Kì í ṣe pípọ̀ tí àwọn ọmọ ogun pọ̀ ní ń gba ọba là;
kì í sì í ṣe ọ̀pọ̀ agbára níí gba jagunjagun là.
17Asán ni igbẹkẹle agbára ẹṣin ogun;
kìí ṣe agbára tí ẹṣin ní, ló lè gbani là.#Jud 9:7; 1 Makab 3:19
18Wò ó! OLUWA ń ṣọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
àní àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,
19kí ó lè gba ọkàn wọn lọ́wọ́ ikú,
kí ó sì mú wọn wà láàyè lákòókò ìyàn.
20Ọkàn wa ní ìrètí lọ́dọ̀ OLUWA;
òun ni olùrànlọ́wọ́ ati ààbò wa.
21A láyọ̀ ninu rẹ̀,
nítorí pé a gbẹ́kẹ̀lé orúkọ mímọ́ rẹ̀.
22OLUWA, jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ wà lórí wa
bí a ti gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 33: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa