Dá mi láre, OLUWA, nítorí ninu ìwà pípé ni mò ń rìn, mo sì gbẹ́kẹ̀lé OLUWA láìṣiyèméjì. Yẹ̀ mí wò, OLUWA, dán mi wò; yẹ inú mi wò, sì ṣe akiyesi ọkàn mi. Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ni mo tẹjúmọ́, mo sì ń fi òtítọ́ bá ọ rìn. N kò jókòó ti àwọn èké, n kò sì gba ìmọ̀ràn àwọn ẹlẹ́tàn; mo kórìíra wíwà pẹlu àwọn aṣebi, n kò sì jẹ́ bá àwọn eniyan burúkú da nǹkan pọ̀. Ọwọ́ mi mọ́, n kò ní ẹ̀bi, OLUWA, mo sì ń jọ́sìn yí pẹpẹ rẹ ká. Mò ń kọ orin ọpẹ́ sókè, mo sì ń ròyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ. OLUWA, mo fẹ́ràn ilé rẹ, tí ò ń gbé, ati ibi tí ògo rẹ wà. Má pa mí run pẹlu àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, má sì gba ẹ̀mí mi pẹlu ti àwọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ ìpànìyàn, àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún iṣẹ́ ibi, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀. Ṣugbọn ní tèmi, èmi ń rìn ninu ìwà pípé; rà mí pada, kí o sì ṣàánú mi. Mo dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú; láwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan ni n óo máa yin OLUWA.
Kà ORIN DAFIDI 26
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 26:1-12
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò