Òun ni àpáta mi, ààbò mi, odi mi, olùdáǹdè mi, asà mi, ẹni tí mo sá di. Òun ni ó tẹrí àwọn eniyan ba lábẹ́ rẹ̀. OLUWA, kí ni eniyan jẹ́, tí o fi ń náání rẹ̀? Kí sì ni ọmọ eniyan tí o fi ń ranti rẹ̀? Eniyan dàbí èémí, ọjọ́ ayé rẹ̀ sì dàbí òjìji tí ń kọjá lọ. OLUWA, fa ojú ọ̀run wá sílẹ̀, kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá, fọwọ́ kan àwọn òkè ńlá, kí wọ́n máa rú èéfín. Jẹ́ kí mànàmáná kọ, kí o sì tú wọn ká, ta ọfà rẹ, kí o tú wọn ká. Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti òkè, kí o yọ mí ninu ibú omi; kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn àjèjì, tí ẹnu wọn kún fún irọ́, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún èké.
Kà ORIN DAFIDI 144
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 144:2-8
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò