ORIN DAFIDI 14

14
Èrè Òmùgọ̀
1Òmùgọ̀ sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun kò sí.”
Wọ́n bàjẹ́, ohun ìríra ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn,
kò sì sí ẹnìkan ninu wọn tí ń ṣe rere.
2OLUWA bojú wo ilẹ̀, láti ọ̀run wá,
ó wo àwọn ọmọ eniyan,
láti mọ̀ bí àwọn kan bá wà tí wọ́n gbọ́n,
tí wọn ń wá Ọlọrun.
3Gbogbo wọn ti ṣìnà,
gbogbo wọn pátá ni wọ́n sì ti bàjẹ́;
kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,
kò sí ẹyọ ẹnìkan ṣoṣo.#Rom 3:10-12
4Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?
Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,
àwọn tí kì í ké pe OLUWA.
5Níbẹ̀ ni a óo ti dẹ́rù bà wọ́n gidigidi,
nítorí Ọlọrun ń bẹ pẹlu àwọn olódodo.
6Ẹ̀yin ń fẹ́ da ètò aláìní rú,
ṣugbọn OLUWA ni ààbò rẹ̀.
7Ìbá ti dára tó kí ìgbàlà Israẹli ti Sioni wá!
Nígbà tí OLUWA bá dá ire àwọn eniyan rẹ̀ pada,
Jakọbu yóo yọ̀, inú Israẹli yóo sì dùn.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 14: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa