ORIN DAFIDI 119:1-24

ORIN DAFIDI 119:1-24 YCE

Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ìgbé ayé wọn kò lábàwọ́n, àní àwọn tí ń rìn gẹ́gẹ́ bí òfin OLUWA. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí wọn ń fi tọkàntọkàn ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Àwọn tí wọn kò dẹ́ṣẹ̀, ṣugbọn tí wọn ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀. O ti pàṣẹ pé kí á fi tọkàntọkàn pa òfin rẹ mọ́, Ìbá ti dára tó tí mo bá lè dúró ṣinṣin ninu ìlànà rẹ! Òun ni ojú kò fi ní tì mí, nítorí pé òfin rẹ ni mò ń tẹ̀lé. N óo yìn ọ́ pẹlu inú mímọ́, bí mo ṣe ń kọ́ ìlànà òdodo rẹ. N óo máa pa òfin rẹ mọ́, má kọ̀ mí sílẹ̀ patapata. Báwo ni ọdọmọkunrin ṣe lè mú kí ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Nípa títẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ ni. Tọkàntọkàn ni mo fi ń ṣe ìfẹ́ rẹ, má jẹ́ kí n ṣìnà kúrò ninu òfin rẹ. Mo ti fi ọ̀rọ̀ rẹ sọ́kàn, kí n má baà ṣẹ̀ ọ́. Ìyìn ni fún ọ, OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ! Mo fi ẹnu mi kéde gbogbo àṣẹ tí o pa. Mo láyọ̀ ninu pípa òfin rẹ mọ́, bí ẹni tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀. N óo máa ṣe àṣàrò ninu òfin rẹ, n óo sì kọjú sí ọ̀nà rẹ. N óo láyọ̀ ninu àwọn ìlànà rẹ, n kò ní gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ. Ṣe ọpọlọpọ oore fún èmi iranṣẹ rẹ, kí n lè wà láàyè, kí n sì máa tẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ. Là mí lójú, kí n lè rí àwọn nǹkan ìyanu tí ó wà ninu òfin rẹ. Àlejò ni mí láyé, má fi òfin rẹ pamọ́ fún mi. Òùngbẹ títẹ̀lé òfin rẹ ń gbẹ ọkàn mi, nígbà gbogbo. O bá àwọn onigbeeraga wí, àwọn ẹni ègún, tí wọn kò pa òfin rẹ mọ́. Mú ẹ̀gàn ati àbùkù wọn kúrò lára mi, nítorí pé mo ti pa òfin rẹ mọ́. Bí àwọn ìjòyè tilẹ̀ gbìmọ̀ràn ọ̀tẹ̀ nítorí mi, sibẹ, èmi iranṣẹ rẹ yóo ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ. Àwọn òfin rẹ ni dídùn inú mi, àwọn ni olùdámọ̀ràn mi.

Verse Images for ORIN DAFIDI 119:1-24

ORIN DAFIDI 119:1-24 - Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ìgbé ayé wọn kò lábàwọ́n,
àní àwọn tí ń rìn gẹ́gẹ́ bí òfin OLUWA.
Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́,
tí wọn ń fi tọkàntọkàn ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
Àwọn tí wọn kò dẹ́ṣẹ̀,
ṣugbọn tí wọn ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
O ti pàṣẹ pé kí á fi tọkàntọkàn pa òfin rẹ mọ́,
Ìbá ti dára tó
tí mo bá lè dúró ṣinṣin ninu ìlànà rẹ!
Òun ni ojú kò fi ní tì mí,
nítorí pé òfin rẹ ni mò ń tẹ̀lé.
N óo yìn ọ́ pẹlu inú mímọ́,
bí mo ṣe ń kọ́ ìlànà òdodo rẹ.
N óo máa pa òfin rẹ mọ́,
má kọ̀ mí sílẹ̀ patapata.

Báwo ni ọdọmọkunrin ṣe lè mú kí ọ̀nà rẹ̀ mọ́?
Nípa títẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ ni.
Tọkàntọkàn ni mo fi ń ṣe ìfẹ́ rẹ,
má jẹ́ kí n ṣìnà kúrò ninu òfin rẹ.
Mo ti fi ọ̀rọ̀ rẹ sọ́kàn,
kí n má baà ṣẹ̀ ọ́.
Ìyìn ni fún ọ, OLUWA,
kọ́ mi ní ìlànà rẹ!
Mo fi ẹnu mi kéde gbogbo àṣẹ tí o pa.
Mo láyọ̀ ninu pípa òfin rẹ mọ́,
bí ẹni tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀.
N óo máa ṣe àṣàrò ninu òfin rẹ,
n óo sì kọjú sí ọ̀nà rẹ.
N óo láyọ̀ ninu àwọn ìlànà rẹ,
n kò ní gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ.

Ṣe ọpọlọpọ oore fún èmi iranṣẹ rẹ,
kí n lè wà láàyè,
kí n sì máa tẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Là mí lójú, kí n lè rí àwọn nǹkan ìyanu
tí ó wà ninu òfin rẹ.
Àlejò ni mí láyé,
má fi òfin rẹ pamọ́ fún mi.
Òùngbẹ títẹ̀lé òfin rẹ ń gbẹ ọkàn mi, nígbà gbogbo.
O bá àwọn onigbeeraga wí, àwọn ẹni ègún,
tí wọn kò pa òfin rẹ mọ́.
Mú ẹ̀gàn ati àbùkù wọn kúrò lára mi,
nítorí pé mo ti pa òfin rẹ mọ́.
Bí àwọn ìjòyè tilẹ̀ gbìmọ̀ràn ọ̀tẹ̀ nítorí mi,
sibẹ, èmi iranṣẹ rẹ yóo ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.
Àwọn òfin rẹ ni dídùn inú mi,
àwọn ni olùdámọ̀ràn mi.ORIN DAFIDI 119:1-24 - Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ìgbé ayé wọn kò lábàwọ́n,
àní àwọn tí ń rìn gẹ́gẹ́ bí òfin OLUWA.
Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́,
tí wọn ń fi tọkàntọkàn ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
Àwọn tí wọn kò dẹ́ṣẹ̀,
ṣugbọn tí wọn ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
O ti pàṣẹ pé kí á fi tọkàntọkàn pa òfin rẹ mọ́,
Ìbá ti dára tó
tí mo bá lè dúró ṣinṣin ninu ìlànà rẹ!
Òun ni ojú kò fi ní tì mí,
nítorí pé òfin rẹ ni mò ń tẹ̀lé.
N óo yìn ọ́ pẹlu inú mímọ́,
bí mo ṣe ń kọ́ ìlànà òdodo rẹ.
N óo máa pa òfin rẹ mọ́,
má kọ̀ mí sílẹ̀ patapata.

Báwo ni ọdọmọkunrin ṣe lè mú kí ọ̀nà rẹ̀ mọ́?
Nípa títẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ ni.
Tọkàntọkàn ni mo fi ń ṣe ìfẹ́ rẹ,
má jẹ́ kí n ṣìnà kúrò ninu òfin rẹ.
Mo ti fi ọ̀rọ̀ rẹ sọ́kàn,
kí n má baà ṣẹ̀ ọ́.
Ìyìn ni fún ọ, OLUWA,
kọ́ mi ní ìlànà rẹ!
Mo fi ẹnu mi kéde gbogbo àṣẹ tí o pa.
Mo láyọ̀ ninu pípa òfin rẹ mọ́,
bí ẹni tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀.
N óo máa ṣe àṣàrò ninu òfin rẹ,
n óo sì kọjú sí ọ̀nà rẹ.
N óo láyọ̀ ninu àwọn ìlànà rẹ,
n kò ní gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ.

Ṣe ọpọlọpọ oore fún èmi iranṣẹ rẹ,
kí n lè wà láàyè,
kí n sì máa tẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Là mí lójú, kí n lè rí àwọn nǹkan ìyanu
tí ó wà ninu òfin rẹ.
Àlejò ni mí láyé,
má fi òfin rẹ pamọ́ fún mi.
Òùngbẹ títẹ̀lé òfin rẹ ń gbẹ ọkàn mi, nígbà gbogbo.
O bá àwọn onigbeeraga wí, àwọn ẹni ègún,
tí wọn kò pa òfin rẹ mọ́.
Mú ẹ̀gàn ati àbùkù wọn kúrò lára mi,
nítorí pé mo ti pa òfin rẹ mọ́.
Bí àwọn ìjòyè tilẹ̀ gbìmọ̀ràn ọ̀tẹ̀ nítorí mi,
sibẹ, èmi iranṣẹ rẹ yóo ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.
Àwọn òfin rẹ ni dídùn inú mi,
àwọn ni olùdámọ̀ràn mi.

Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú ORIN DAFIDI 119:1-24