ORIN DAFIDI 114
114
Orin Ìrékọjá
1Nígbà tí Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti,
tí àwọn ọmọ Jakọbu jáde kúrò láàrin àwọn tí ń sọ èdè àjèjì,
2Juda di ilé mímọ́ rẹ̀,
Israẹli sì di ìjọba rẹ̀.#Eks 12:51
3Òkun rí i, ó sá,
Jọdani rí i, ó pada sẹ́yìn.#(a) Eks 114:21 (b) Joṣ 3:16
4Àwọn òkè ńláńlá ń fò bí àgbò,
àwọn òkè kéékèèké ń fò bí ọmọ aguntan.
5Kí ló dé, tí o fi sá, ìwọ òkun?
Kí ló ṣẹlẹ̀ tí o fi pada sẹ́yìn, ìwọ Jọdani?
6Ẹ̀yin òkè ńlá, kí ló dé tí ẹ fi fò bí àgbò?
Ẹ̀yin òkè kéékèèké, kí ló ṣẹlẹ̀ tí ẹ fi fò bí ọmọ aguntan?
7Wárìrì níwájú OLUWA, ìwọ ilẹ̀,
wárìrì níwájú Ọlọrun Jakọbu.
8Ẹni tí ó sọ àpáta di adágún omi,
tí ó sì sọ akọ òkúta di orísun omi.#Eks 17:1-7; Nọm 20:2-13
Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:
ORIN DAFIDI 114: YCE
Ìsàmì-sí
Pín
Daako
![None](/_next/image?url=https%3A%2F%2Fimageproxy.youversionapi.com%2F58%2Fhttps%3A%2F%2Fweb-assets.youversion.com%2Fapp-icons%2Fyo.png&w=128&q=75)
Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀
Bible Society of Nigeria © 1900/2010