ORIN DAFIDI 106:13-31

ORIN DAFIDI 106:13-31 YCE

Kò pẹ́ tí wọ́n tún fi gbàgbé iṣẹ́ rẹ̀, wọn kò sì dúró gba ìmọ̀ràn rẹ̀. Wọ́n ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ní aṣálẹ̀, wọ́n sì dán Ọlọrun wò. Ó fún wọn ní ohun tí wọ́n bèèrè, ṣugbọn ó fi àìsàn ajẹnirun ṣe wọ́n. Nígbà tí wọ́n ṣe ìlara sí Mose ninu ibùdó, ati sí Aaroni, ẹni mímọ́ OLÚWA. Ilẹ̀ yanu, ó gbé Datani mì, ó sì bo Abiramu ati àwọn tí ó tẹ̀lé e mọ́lẹ̀. Iná sọ láàrin wọn, ó sì jó àwọn eniyan burúkú náà run. Wọ́n yá ère ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù ní Horebu, wọ́n sì bọ ère tí wọ́n dà. Wọ́n gbé ògo Ọlọrun fún ère mààlúù tí ń jẹ koríko. Wọ́n gbàgbé Ọlọrun, Olùgbàlà wọn, tí ó ṣe iṣẹ́ ribiribi ní Ijipti, ó ṣe, iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu, ati ohun ẹ̀rù lẹ́bàá òkun pupa. Nítorí náà ni ó ṣe wí pé òun yóo pa wọ́n run, bí kì í bá ṣe ti Mose, àyànfẹ́ rẹ̀, tí ó dúró níwájú rẹ̀, tí ó sì ṣìpẹ̀, láti yí ibinu OLUWA pada, kí ó má baà pa wọ́n run. Wọn kò bìkítà fún ilẹ̀ dáradára náà, wọn kò sì ní igbagbọ ninu ọ̀rọ̀ OLUWA. Wọ́n ń kùn ninu àgọ́ wọn, wọn kò sì fetí sí ohùn OLUWA. Nítorí náà, ó gbé ọwọ́ sókè, ó búra fún wọn pé òun yóo jẹ́ kí wọ́n kú sí aṣálẹ̀, ati pé òun yóo fọ́n àwọn ìran wọn káàkiri àwọn orílẹ̀-èdè. Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali ti Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí wọ́n rú sí òkú. Wọ́n fi ìwà burúkú wọn mú OLUWA bínú, àjàkálẹ̀ àrùn sì bẹ́ sílẹ̀ láàrin wọn. Nígbà náà ni Finehasi dìde, ó bẹ̀bẹ̀ fún wọn, àjàkálẹ̀ àrùn sì dáwọ́ dúró. A sì kà á kún òdodo fún un, láti ìrandíran títí lae.