Aláriwo ni obinrin tí kò gbọ́n, oníwọ̀ra ni, kò sì ní ìtìjú. Á máa jókòó lẹ́nu ọ̀nà ilé rẹ̀, á jókòó ní ibi tí ó ga láàrin ìlú. A máa kígbe pe àwọn tí ń kọjá lọ, àwọn tí ń bá tiwọn lọ jẹ́ẹ́jẹ́ wọn, pé, “Ẹni tí ó bá jẹ́ aláìmọ̀kan, kí ó máa bọ̀!” Ó sì wí fún àwọn òmùgọ̀ pé, “Omi tí eniyan bá jí mu a máa dùn, oúnjẹ tí a bá jí jẹ, oyinmọmọ ni.” Àwọn tí wọ́n bá yà sọ́dọ̀ rẹ̀ kò ní mọ̀ pé ikú wà ní ilé rẹ̀, ati pé inú isà òkú ni àwọn tí wọ́n bá wọ ilé rẹ̀ wọ̀.
Kà ÌWÉ ÒWE 9
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ÌWÉ ÒWE 9:13-18
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò