Gba ẹ̀wù ẹni tí ó bá ṣe onídùúró fún àlejò, gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tí kò mọ̀ rí. Oúnjẹ tí a bá rí lọ́nà èrú máa ń dùn lẹ́nu eniyan, ṣugbọn nígbà tí a bá jẹ ẹ́ tán, ẹnu ẹni a máa kan. Ìmọ̀ràn níí fìdí ètò múlẹ̀, gba ìtọ́sọ́nà kí o tó lọ jagun. Ẹni tí ó ń ṣe òfófó káàkiri a máa tú ọpọlọpọ àṣírí, nítorí náà má ṣe bá ẹlẹ́jọ́ kẹ́gbẹ́. Bí eniyan bá ń fi baba tabi ìyá rẹ̀ bú, àtùpà rẹ̀ yóo kú láàrin òkùnkùn biribiri. Ogún tí a fi ìkánjú kójọ níbẹ̀rẹ̀, kì í ní ibukun nígbẹ̀yìn. Má sọ pé o fẹ́ fi burúkú san burúkú, gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, yóo sì gbà ọ́. Ayédèrú òṣùnwọ̀n jẹ́ ohun ìríra lójú OLUWA, ìwọ̀n èké kò dára. OLUWA ní ń tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni, eniyan kò lè ní òye ọ̀nà ara rẹ̀. Ronú jinlẹ̀ kí o tó jẹ́jẹ̀ẹ́ fún OLUWA, kí o má baà kábàámọ̀ rẹ̀. Ọba tó gbọ́n a máa fẹ́ eniyan burúkú dànù, a sì lọ̀ wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ̀mí eniyan ni fìtílà OLUWA, tíí máa wá gbogbo kọ́lọ́fín inú rẹ̀ kiri. Ìfẹ́ ati òtítọ́ níí mú kí ọba pẹ́, òdodo níí sì ń gbé ìjọba rẹ̀ ró. Agbára ni ògo ọ̀dọ́, ewú sì ni ẹwà àgbà. Ìjìyà tó fa ọgbẹ́ a máa mú ibi kúrò, pàṣán a máa mú kí inú mọ́.
Kà ÌWÉ ÒWE 20
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ÌWÉ ÒWE 20:16-30
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò