MIKA Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ọ̀rọ̀ Iṣaaju
Ní àkókò wolii Aisaya ni Mika, ará ìlú kan ní ilẹ̀ Juda, jẹ́ wolii. Ó dá a lójú pé, àsọtẹ́lẹ̀ Amosi nípa ìyà tí yóo dé bá Israẹli kò ní ṣaláì ṣẹlẹ̀ sí Juda náà, fún ìdí kan náà–Ọlọrun yóo fìyà jẹ àwọn náà nítorí ìríra ìwà ìdájọ́ èké wọn. Ṣugbọn Mika ṣe ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé ati àwọn àpẹẹrẹ fún ìrètí lọ́jọ́ iwájú.
Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ pataki tí ó yẹ kí eniyan kíyèsí ni alaafia tí ó wà fún eniyan nípa sísúnmọ́ Ọlọrun (4:1-4); àsọtẹ́lẹ̀ nípa ọba pataki kan tí wọn yóo bí láti inú ìran Dafidi, tí yóo sì mú alaafia wá sí orílẹ̀-èdè náà (5:2-5a); ní orí 6:8, Mika ṣe àlàyé ní ṣókí lórí ohun tí ọ̀rọ̀ gbogbo àwọn wolii Israẹli dá lé lórí pé: “Ohun tí Ọlọrun fẹ́ kí á ṣe nìyí: kí á ṣe ohun tí ó tọ́, kí á fi ìfẹ́ tí ó dúró ṣinṣin hàn, kí á sì wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹlu Ọlọrun wa.”
Àwọn Ohun tí ó wà ninu Ìwé yìí ní Ìsọ̀rí-ìsọ̀rí
Ìdájọ́ lórí Israẹli ati Juda 1:1–3:12
Ìyípadà sí rere ati alaafia 4:1–5:15
Ọ̀rọ̀ ìkìlọ̀ ati ìrètí 6:1–7:20

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

MIKA Ọ̀rọ̀ Iṣaaju: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀