“Lẹ́yìn náà, nígbà tí ó bá yá, n óo tú ẹ̀mí mi jáde sára gbogbo eniyan, àwọn ọmọkunrin ati àwọn ọmọbinrin yín yóo máa sọ àsọtẹ́lẹ̀, àwọn àgbààgbà yín yóo máa lá àlá, àwọn ọdọmọkunrin yín yóo sì máa ríran. Bákan náà, nígbà tí àkókò bá tó, n óo tú ẹ̀mí mi jáde sára àwọn iranṣẹkunrin ati àwọn iranṣẹbinrin yín. “Ìtàjẹ̀sílẹ̀ yóo pọ̀, n óo sì fi iná, ati òpó èéfín sí ojú ọ̀run, ati sórí ilẹ̀ ayé; yóo jẹ́ ìkìlọ̀ fun yín. Oòrùn yóo ṣókùnkùn, òṣùpá yóo pọ́n rẹ̀bẹ̀tẹ̀ bí ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ OLUWA tí ó lẹ́rù tó dé. Ṣugbọn gbogbo àwọn tí wọ́n bá ké pe orúkọ OLUWA ni a óo gbàlà. Àwọn kan yóo sá àsálà ní òkè Sioni, ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí OLUWA ti sọ, àwọn tí OLUWA pè yóo sì wà lára àwọn tí wọn yóo sá àsálà.
Kà JOẸLI 2
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JOẸLI 2:28-32
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò