OLUWA ní, “Ègún ni fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé eniyan, tí ó fi ẹlẹ́ran ara ṣe agbára rẹ̀; tí ọkàn rẹ̀ yipada kúrò lọ́dọ̀ èmi OLUWA. Ó dàbí igbó ṣúúrú ninu aṣálẹ̀, nǹkan rere kan kò lè ṣẹlẹ̀ sí i. Ninu ilẹ̀ gbígbẹ, ninu aṣálẹ̀ ni ó wà, ninu ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò lè gbé. “Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, tí ó fi OLUWA ṣe àgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀. Yóo dàbí igi tí a gbìn sí ipa odò, tí ó ta gbòǹgbò kan ẹ̀bá odò. Ẹ̀rù kò ní bà á nígbà tí ẹ̀ẹ̀rùn bá dé, nítorí pé ewé rẹ̀ yóo máa tutù minimini. Kò ní páyà lákòókò ọ̀gbẹlẹ̀, nígbà gbogbo ni yóo sì máa so. “Ọkàn eniyan kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ìwà ìbàjẹ́ sì kún inú rẹ̀; ta ni ó lè mọ èrò ọkàn eniyan?
Kà JEREMAYA 17
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: JEREMAYA 17:5-9
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò