AISAYA 40

40
Ọ̀rọ̀ Ìtùnú fún Àwọn Ọmọ Israẹli
1Ọlọrun yín ní, “Ẹ tù wọ́n ninu,
ẹ tu àwọn eniyan mi ninu.
2Ẹ bá Jerusalẹmu sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́
ẹ ké sí i pé, ogun jíjà rẹ̀ ti parí,
a ti dárí àìṣedéédé rẹ̀ jì í.
OLUWA ti jẹ ẹ́ níyà ní ìlọ́po meji nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
3Ẹ gbọ́ ohùn akéde kan tí ń wí pé,#Sir 48:10; Bar 5:7; Mat 3:3; Mak 1:3; Joh 1:23
“Ẹ tún ọ̀nà OLUWA ṣe ninu aginjù,
ẹ la òpópónà títọ́ fún Ọlọrun wa ninu aṣálẹ̀.
4Gbogbo àfonífojì ni a óo ru sókè,
a óo sì sọ àwọn òkè ńlá ati òkè kéékèèké di pẹ̀tẹ́lẹ̀:
Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ́ ni yóo di títọ́,
ọ̀nà gbágun-gbàgun yóo sì di títẹ́jú.
5Ògo OLUWA yóo farahàn,#Luk 3:4-6
gbogbo eniyan yóo sì jọ fojú rí i.
OLUWA ni ó fi ẹnu ara rẹ̀ sọ bẹ́ẹ̀.”
6Mo gbọ́ ohùn kan tí ń wí pé, “Kígbe!”
Mo bá bèèrè pé,
“Igbe kí ni kí n ké?”
Ó ní, “Kígbe pé, koríko ṣá ni gbogbo eniyan,
gbogbo ẹwà sì dàbí òdòdó inú pápá.
7Koríko a máa rọ, òdòdó a sì máa rẹ̀
nígbà tí OLUWA bá fẹ́ afẹ́fẹ́ lù ú.
Dájúdájú koríko ni eniyan.
8Koríko a máa rọ,#Jak 1:10-11; 1 Pet 1:24-25
òdòdó a sì máa rẹ̀;
ṣugbọn ọ̀rọ̀ Ọlọrun wa dúró títí lae.”
9Gun orí òkè gíga lọ, ìwọ Sioni,
kí o máa kéde ìyìn rere.
Gbé ohùn rẹ sókè pẹlu agbára Jerusalẹmu,
ìwọ tí ò ń kéde ìyìn rere
ké sókè má ṣe bẹ̀rù;
sọ fún àwọn ìlú Juda pé,
“Ẹ wo Ọlọrun yín.”
10Ẹ wò ó! OLUWA Ọlọrun ń bọ̀ pẹlu agbára#Ais 62:11; Ifi 22:12
ipá rẹ̀ ni yóo fi máa ṣe àkóso.
Ẹ wò ó! Èrè rẹ̀ ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ̀san rẹ̀ sì ń bẹ níwájú rẹ̀.
11Yóo bọ́ agbo ẹran bí olùṣọ́-aguntan.#Isi 34:15; Joh 10:11
Yóo kó àwọn ọ̀dọ́ aguntan jọ sí apá rẹ̀,
yóo gbé wọn mọ́ àyà rẹ̀.
Yóo sì máa fi sùúrù da àwọn tí wọn lọ́mọ lẹ́yìn láàrin wọn.
OLUWA Kò Ní Àfijọ
12Ta ló lè fi kòtò ọwọ́ wọn omi òkun?
Ta ló lè fìka wọn ojú ọ̀run,
Kí ó kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé
sinu òṣùnwọ̀n?
Ta ló lè gbé àwọn òkè ńlá ati àwọn kéékèèké sórí ìwọ̀n?
13Ta ló darí Ẹ̀mí OLUWA,#Rom 11:34; 1 Kọr 2:16
ta ló sì tọ́ ọ sọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14Ọwọ́ ta ni OLUWA ti gba ìmọ̀ràn tí ó fi ní òye,
ta ló kọ́ ọ bí wọ́n ṣe ń dájọ́ ẹ̀tọ́,
tí ó kọ́ ọ ní ìmọ̀,
tí ó sì fi ọ̀nà òye hàn án?
15Wò ó, àwọn orílẹ̀-èdè dàbí ìkán omi kan ninu garawa omi,#Ọgb 11:22; Sir 10:16-17
ati bí ẹyọ eruku kan lórí òṣùnwọ̀n.
Ẹ wò ó, ó mú àwọn erékùṣù lọ́wọ́ bí àtíkè.
16Gbogbo igi igbó Lẹbanoni kò tó fún iná ẹbọ,
bẹ́ẹ̀ ni ẹranko ibẹ̀ kò tó fún ẹbọ sísun.
17Gbogbo orílẹ̀-èdè kò tó nǹkan níwájú rẹ̀,
wọn kò jámọ́ nǹkan lójú rẹ̀, òfo ni wọ́n.
18Ta ni ẹ lè fi Ọlọrun wé,
tabi kí ni ẹ lè fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19Ṣé oriṣa ni! Tí oníṣẹ́ ọwọ́ ṣe;#A. Apo 17:29
tí alágbẹ̀dẹ wúrà yọ́ wúrà bò
tí ó sì fi fadaka ṣe ẹ̀wọ̀n fún?
20Ẹni tí ó bá talaka, tí kò lágbára nǹkan ìrúbọ,#Ọgb 13:11-19
a wá igi tí kò lè rà, tí kò sì lè ju;
a wá agbẹ́gilére tí ó mọṣẹ́,
láti bá a gbẹ́ ère tí kò lè paradà.
21Ṣé ẹ kò tíì mọ̀?
Ẹ kò sì tíì gbọ́?
Ṣé wọn kò sọ fun yín láti ìbẹ̀rẹ̀,
kò sì ye yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, pé:
22Òun ni ó jókòó lókè àyíká ayé,
àwọn eniyan inú rẹ̀ sì dàbí tata lójú rẹ̀.
Òun ni ó ta awọsanma bí aṣọ títa,
ó sì ta á bí àgọ́, ó ń gbébẹ̀.
23Ẹni tí ó sọ àwọn ọba di ẹni ilẹ̀,
ó sọ àwọn olóyè ayé di asán.
24Wọ́n fẹ́rẹ̀ má ì tíì gbìn wọ́n,
wọ́n fẹ́rẹ̀ má ì tíì ta gbòǹgbò wọlẹ̀;
nígbà tí ó fẹ́ afẹ́fẹ́ lù wọ́n,
tí wọ́n fi rọ bí ewéko,
tí ìjì sì gbé wọn lọ bí àgékù koríko.
25Ta ni ẹ óo wá fi mí wé,
tí n óo sì dàbí rẹ̀?
Èmi Ẹni Mímọ́ ni mo bèèrè bẹ́ẹ̀.
26Ẹ gbójú sókè kí ẹ wo ojú ọ̀run,#Bar 3:34-35
ta ni ó dá àwọn nǹkan tí ẹ rí wọnyi?
Ẹni tí ó kó àwọn ìràwọ̀ sójú ọ̀run bí ọmọ ogun,
tí ó ń pè wọ́n jáde lọ́kọ̀ọ̀kan,
tí ó sì mọ olukuluku mọ́ orúkọ rẹ̀.
Nítorí bí ipá rẹ̀ ti tó,
ati bí agbára rẹ̀ ti pọ̀ tó,
ẹyọ ọ̀kan ninu wọn kò di àwátì.
27Kí ló dé, Jakọbu, tí o fi ń rojọ́?
Kí ló ṣe ọ́, Israẹli, tí o fi ń sọ pé,
“OLUWA kò mọ ohun tí ń ṣe mí,
Ọlọrun kò sì bìkítà nípa ẹ̀tọ́ mi.”
28Ṣé o kò tíì mọ̀,
o kò sì tíì gbọ́
pé Ọlọrun ayérayé ni OLUWA,
Ẹlẹ́dàá gbogbo ayé.
Kì í rẹ̀ ẹ́, bẹ́ẹ̀ ni agara kì í dá a.
Àwámárìídìí ni òye rẹ̀.
29A máa fún aláàárẹ̀ ní okun.
A sì máa fún ẹni tí kò lágbára ní agbára.
30Yóo rẹ àwọn ọ̀dọ́ pàápàá, agara óo sì dá wọn,
àwọn ọdọmọkunrin yóo tilẹ̀ ṣubú lulẹ̀ patapata.
31Ṣugbọn àwọn tí ó bá dúró de OLUWA
yóo máa gba agbára kún agbára.
Wọn óo máa fi ìyẹ́ fò lọ sókè bí ẹyẹ idì.
Wọn óo máa sáré, agara kò ní dá wọn;
wọn óo máa rìn, kò sì ní rẹ̀ wọ́n.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

AISAYA 40: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀