Ẹ óo máa ronú ìnira tí ẹ ti ní pé: “Níbo ni akọ̀wé wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó orí wà? Níbo sì ni ẹni tí ń ka ilé ìṣọ́ wà?” Ẹ kò ní rí àwọn aláfojúdi náà mọ́, àwọn tí wọn ń fọ èdè tí kò ní ìtumọ̀ si yín, tí wọn ń kólòlò ní èdè tí ẹ kò gbọ́. Ẹ wo Sioni, ìlú tí a yà sọ́tọ̀ fún àjọ̀dún. Ẹ óo fi ojú rí Jerusalẹmu, ibùgbé alaafia, tí àgọ́ rẹ̀ kò ní ṣídìí, tí èèkàn tí a fi kàn án mọ́lẹ̀ kò ní hú laelae, bẹ́ẹ̀ ni okùn tí a fi so ó mọ́lẹ̀ kò ní já. Ṣugbọn níbẹ̀ ni OLUWA, ninu ògo rẹ̀, yóo jẹ́ odò ńlá ati odò tí ń ṣàn fún wa; níbi tí ọkọ̀ ọlọ́pọ́n kò lè dé, ọkọ̀ ojú omi kò sì ní lè kọjá níbẹ̀.
Kà AISAYA 33
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: AISAYA 33:18-21
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò