Ọ̀dọ́
Ìgboyà: Àgbéyẹ̀wò Ìgboyà Ìgbàgbọ́ Àwọn Ènìyàn Aláìpé
Ìgboyà kò nílò láti jẹ́ ohun tí ó bùyààrì tí a sì ní láti pariwo rẹ̀ fún ayé rí; ó kàn jẹ́ ìgbésẹ̀ láti mú ohunkóhun tí o ní wá fún Jésù àti níní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Rẹ̀ lórí àbájáde wọn. Wá jẹ́ ká jọ rìn ìrìn-àjò ọlọ́jọ́ méje láti wo bí àwọn ènìyàn aláìpé ṣe ní ìgbàgbọ́ tí ó lágbára.
Ka Májẹ̀mú Titun Já
Nínú ètò yìí, wà á ka Májẹ̀mú Titun já láàárín ọdún kan.
Mọ: Ojọ́ Mẹ́wàá láti Mọ Ẹni Tí O Jẹ́
Ó lè rọrùn láti ṣìnà nínú ohun táwọn èèyàn mọ̀ ẹ́ sí, kó o sì pàdánù ẹni táwọn èèyàn mọ̀ ẹ́ sí. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ ohun tó pọ̀ nípa irú ẹni tó o jẹ́ àti irú ẹni tí Ọlọ́run dá ẹ láti jẹ́. Ìfọkànsìn ọlọ́jọ́ mẹ́wàá yìí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti rìnrìn àjò lọ síbi tí wàá ti mọ irú ẹni tó o jẹ́ gan-an.
Ètò Olúwa Fún Ayéè
Kíni ètò Olúwa fún ayéè rẹ? Èyí jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìbéèrè tí a maá ń bèrè gẹ́gẹ́ bíi ọmọ-lẹ́yìn-Kristi. Ṣùgbọ́n, tí a bá ma jẹ olóòótọ́, ìrònú wa nípa ètò Olúwa fún ayé wa lè lágbára ju ọgbọ́n orí wa lọ. Nínú ètò Bíbélì ọlọ́jọ́-mẹ́fà yìí, a ó kọ́ọ wípé ètò Olúwa kò le bí a ti lérò, ṣùgbọ́n ó dára ní gbogbo ọ̀nà ju bí a ti lérò
Ìbínú
Gbogbo wa la máa n bínú! Ìdáhùn rẹ sí ìbínú dá lórí gbígbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run àti ṣíṣàrò lórí Ọ̀rọ Rẹ̀. Wo ètò kíkà Ìgbẹ́kẹ̀lé lẹ́gbẹ̀ẹ́ àkọ́lé Ìbínú. Àwọn ẹsẹ̀ tí ó tẹ̀lé e, tí a bá fi wọ́n ṣe àkọ́sórí, lè ràn ọ́ l'ọ́wọ́ láti dáhùn sí ìbínú l'ọ́na tó tọ́. Jẹ́ kí ìgbésí ayé rẹ yípadà nípasẹ fífi Ìwé Mímọ́ se àkọ́sórí! Fún ètò kíkún fún fífi Ìwé Mímọ́ se àkọ́sórí, lọ sí www.MemLoK.com
Tani Jésù?
Jésù ní àárín gbùngbùn ìgbàgbọ́ Krìstẹ́nì, ètò ọlọ́jọ́ 5 yìí mú wa lọ inú ọ̀gbun Ẹni tí ṣe: Olùdárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, Ọ̀rẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, Ìmọ́lẹ̀, Oníṣẹ́-ìyanu, Olúwa-tó-Jíìnde.