Àwọn Òdọ́ Àgbàlagbà
Ìtọ́sọ́nà Àtọ̀runwá
Lójojúmọ́, a ma ńṣe àwọn àṣàyàn tó ń tọ́ ipa nínú ìtàn ìgbésí ayé wa. Báwo ni ìtàn ìgbésí ayé rẹ yóò ti rí tí o bá ṣe àwọn àṣàyàn tó dára? Nínú Ètò Bíbélì Ìtọ́sọ́nà Àtọ̀runwá, gbajú-gbajà ònkọ̀wé New York Times àti Olùṣọ́àgùntàn àgbà ní ìjọ Life.Church, Craig Groeschel, máa gbà ọ́ níyànjú pẹ̀lú àwọn ìlànà méje tí a fà jáde látinú ìwé Ìtọ́sọ́nà Àtọ̀runwá fún ìrànlọ́wọ́ láti ṣe àwárí ọgbọ́n Ọlọ́run fún àwọn ìpinnu tí à ńṣe lójojúmọ́. Ṣe àwárí àwọn ìtọ́ni ti ẹ̀mí tí o nílò láti gbé ìgbésí ayé tó bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run.
Ka Májẹ̀mú Titun Já
Nínú ètò yìí, wà á ka Májẹ̀mú Titun já láàárín ọdún kan.
Ètò Olúwa Fún Ayéè
Kíni ètò Olúwa fún ayéè rẹ? Èyí jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìbéèrè tí a maá ń bèrè gẹ́gẹ́ bíi ọmọ-lẹ́yìn-Kristi. Ṣùgbọ́n, tí a bá ma jẹ olóòótọ́, ìrònú wa nípa ètò Olúwa fún ayé wa lè lágbára ju ọgbọ́n orí wa lọ. Nínú ètò Bíbélì ọlọ́jọ́-mẹ́fà yìí, a ó kọ́ọ wípé ètò Olúwa kò le bí a ti lérò, ṣùgbọ́n ó dára ní gbogbo ọ̀nà ju bí a ti lérò