O. Daf 147:7-11
O. Daf 147:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Fi ọpẹ́ kọrin sí OLúWA fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run. Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké. Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin OLúWA ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
O. Daf 147:7-11 Yoruba Bible (YCE)
Ẹ kọ orin ọpẹ́ sí OLUWA, ẹ fi hapu kọ orin dídùn sí Ọlọrun wa. Ẹni tí ó fi ìkùukùu bo ojú ọ̀run, ó pèsè òjò fún ilẹ̀, ó mú koríko hù lórí òkè. Òun ni ó ń fún àwọn ẹranko ní oúnjẹ, tí ó sì ń bọ́ ọmọ ẹyẹ ìwò, tí ó ń ké. Kì í ṣe agbára ẹṣin ni inú rẹ̀ dùn sí, kì í sì í ṣe inú agbára eniyan ni ayọ̀ rẹ̀ wà. Ṣugbọn inú OLUWA dùn sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àwọn tí ó ní ìrètí ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
O. Daf 147:7-11 Bibeli Mimọ (YBCV)
Ẹ fi ọpẹ kọrin si Oluwa; kọrin iyìn si Ọlọrun wa lara duru: Ẹniti o fi awọsanma bò oju ọrun, ẹniti o pèse òjo fun ilẹ, ti o mu koriko dàgba lori awọn òke nla. O fi onjẹ ẹranko fun u ati fun ọmọ iwò ti ndún. Kò ṣe inudidùn si agbara ẹṣin: kò ṣe inudidùn si ẹsẹ ọkunrin. Oluwa nṣe inudidùn si awọn ti o bẹ̀ru rẹ̀, si awọn ti nṣe ireti ãnu rẹ̀.
O. Daf 147:7-11 Yoruba Bible (YCE)
Ẹ kọ orin ọpẹ́ sí OLUWA, ẹ fi hapu kọ orin dídùn sí Ọlọrun wa. Ẹni tí ó fi ìkùukùu bo ojú ọ̀run, ó pèsè òjò fún ilẹ̀, ó mú koríko hù lórí òkè. Òun ni ó ń fún àwọn ẹranko ní oúnjẹ, tí ó sì ń bọ́ ọmọ ẹyẹ ìwò, tí ó ń ké. Kì í ṣe agbára ẹṣin ni inú rẹ̀ dùn sí, kì í sì í ṣe inú agbára eniyan ni ayọ̀ rẹ̀ wà. Ṣugbọn inú OLUWA dùn sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àwọn tí ó ní ìrètí ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
O. Daf 147:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Fi ọpẹ́ kọrin sí OLúWA fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run. Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké. Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin OLúWA ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.