Owe 21:1-16
Owe 21:1-16 Bibeli Mimọ (YBCV)
AIYA ọba mbẹ lọwọ Oluwa bi odò omi; on a si dari rẹ̀ si ìbikibi ti o wù u. Gbogbo ọ̀na enia li o dara li oju ara rẹ̀: ṣugbọn Oluwa li o nṣe amọ̀na ọkàn. Lati ṣe ododo ati idajọ, o ṣe itẹwọgba fun Oluwa jù ẹbọ lọ. Gangan oju, ati igberaga aiya, ati itulẹ̀ enia buburu, ẹ̀ṣẹ ni. Ìronu alãpọn si kiki ọ̀pọ ni; ṣugbọn ti olukuluku ẹniti o yara, si kiki aini ni. Ini iṣura nipa ahọn eke, o jẹ ẽmi ti a ntì sihin tì sọhun lọwọ awọn ti nwá ikú kiri. Iwa-agbara awọn enia buburu ni yio pa wọn run: nitori ti nwọn kọ̀ lati ṣe idajọ. Ẹnikẹni ti o nrìn ọ̀na ayidayida, enia buburu ni; ṣugbọn oninu funfun ni iṣẹ rẹ̀ tọ́. O san lati joko ni igun òke àja, jù pẹlu onija obinrin lọ ninu ile ajumọgbe. Ọkàn enia buburu nwá ibi kiri: aladugbo rẹ̀ kò ri ojurere li oju rẹ̀. Nigbati a ba jẹ ẹlẹgàn ni ìya, a sọ òpe di ọlọgbọ́n: nigbati a ba si nkọ́ ọlọgbọ́n, on o ma ni ìmọ. Olododo kiyesi ile enia buburu: pe ẹnikan wà ti yio bì enia buburu ṣubu sinu iparun. Ẹnikẹni ti o ba di eti rẹ̀ si igbe olupọnju, ontikararẹ̀ yio ke pẹlu: ṣugbọn a kì yio gbọ́. Ọrẹ ikọkọ, o tù ibinu: ati ẹ̀bun ni iṣẹpo-aṣọ, o tù ibinu lile. Ayọ̀ ni fun olododo lati ṣe idajọ: ṣugbọn iparun ni fun awọn oniṣẹ ẹ̀ṣẹ. Ẹniti o ba yà kuro li ọ̀na oye, yio ma gbe inu ijọ awọn okú.
Owe 21:1-16 Yoruba Bible (YCE)
Orísun omi ni ọkàn ọba lọ́wọ́ OLUWA, ibi tí ó bá wu Oluwa ni ó ń darí rẹ̀ sí. Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó dára lójú ara rẹ̀, ṣugbọn ọkàn ni OLUWA ń wò. Kí eniyan ṣe òdodo ati ẹ̀tọ́, sàn ju ẹbọ lọ lójú OLUWA. Bíi fìtílà ẹni ibi ni gbígbé ojú gangan ati ìgbéraga, ẹ̀ṣẹ̀ sì ni wọ́n. Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító. Fífi èké kó ìṣúra jọ dàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú. Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù, nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́. Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún, ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́. Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà, ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ. Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́, àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀. Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n, tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i. Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú, eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka, òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn. Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu, àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà. Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn, ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi. Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òye yóo sinmi láàrin àwọn òkú.
Owe 21:1-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ OLúWA; a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi. Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀ ṣùgbọ́n, OLúWA ló ń díwọ̀n ọkàn. Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí OLúWA ju ẹbọ lọ. Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga, ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni! Ètè àwọn olóye jásí èrè bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá. Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́ jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú. Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ, nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́. Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́. Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà. Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀. Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n, nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀. Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú, òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú; ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́. Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò: àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá, dẹ́kun ìbínú líle. Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́: ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀. Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye, yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
Owe 21:1-16 Bibeli Mimọ (YBCV)
AIYA ọba mbẹ lọwọ Oluwa bi odò omi; on a si dari rẹ̀ si ìbikibi ti o wù u. Gbogbo ọ̀na enia li o dara li oju ara rẹ̀: ṣugbọn Oluwa li o nṣe amọ̀na ọkàn. Lati ṣe ododo ati idajọ, o ṣe itẹwọgba fun Oluwa jù ẹbọ lọ. Gangan oju, ati igberaga aiya, ati itulẹ̀ enia buburu, ẹ̀ṣẹ ni. Ìronu alãpọn si kiki ọ̀pọ ni; ṣugbọn ti olukuluku ẹniti o yara, si kiki aini ni. Ini iṣura nipa ahọn eke, o jẹ ẽmi ti a ntì sihin tì sọhun lọwọ awọn ti nwá ikú kiri. Iwa-agbara awọn enia buburu ni yio pa wọn run: nitori ti nwọn kọ̀ lati ṣe idajọ. Ẹnikẹni ti o nrìn ọ̀na ayidayida, enia buburu ni; ṣugbọn oninu funfun ni iṣẹ rẹ̀ tọ́. O san lati joko ni igun òke àja, jù pẹlu onija obinrin lọ ninu ile ajumọgbe. Ọkàn enia buburu nwá ibi kiri: aladugbo rẹ̀ kò ri ojurere li oju rẹ̀. Nigbati a ba jẹ ẹlẹgàn ni ìya, a sọ òpe di ọlọgbọ́n: nigbati a ba si nkọ́ ọlọgbọ́n, on o ma ni ìmọ. Olododo kiyesi ile enia buburu: pe ẹnikan wà ti yio bì enia buburu ṣubu sinu iparun. Ẹnikẹni ti o ba di eti rẹ̀ si igbe olupọnju, ontikararẹ̀ yio ke pẹlu: ṣugbọn a kì yio gbọ́. Ọrẹ ikọkọ, o tù ibinu: ati ẹ̀bun ni iṣẹpo-aṣọ, o tù ibinu lile. Ayọ̀ ni fun olododo lati ṣe idajọ: ṣugbọn iparun ni fun awọn oniṣẹ ẹ̀ṣẹ. Ẹniti o ba yà kuro li ọ̀na oye, yio ma gbe inu ijọ awọn okú.
Owe 21:1-16 Yoruba Bible (YCE)
Orísun omi ni ọkàn ọba lọ́wọ́ OLUWA, ibi tí ó bá wu Oluwa ni ó ń darí rẹ̀ sí. Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó dára lójú ara rẹ̀, ṣugbọn ọkàn ni OLUWA ń wò. Kí eniyan ṣe òdodo ati ẹ̀tọ́, sàn ju ẹbọ lọ lójú OLUWA. Bíi fìtílà ẹni ibi ni gbígbé ojú gangan ati ìgbéraga, ẹ̀ṣẹ̀ sì ni wọ́n. Dájúdájú èrò ẹni tí ó ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn yóo yọrí sí ọ̀pọ̀, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń kánjú jù kò ní ní ànító. Fífi èké kó ìṣúra jọ dàbí lílé ìkùukùu, ó sì jẹ́ tàkúté ikú. Ìwà ipá àwọn ẹni ibi ni yóo gbá wọn dànù, nítorí pé wọ́n kọ̀ láti ṣe òtítọ́. Ọ̀nà ẹlẹ́bi kì í gún, ṣugbọn ìrìn aláìlẹ́bi a máa tọ́. Ó sàn láti máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà, ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ. Ibi ni ọkàn eniyan burúkú máa ń fẹ́, àwọn aládùúgbò rẹ̀ kì í sìí rí ojurere rẹ̀. Ìjìyà ẹlẹ́yà a máa mú kí òpè gbọ́n, tí a bá ń kọ́ ọlọ́gbọ́n, yóo ní ìmọ̀ sí i. Olódodo ṣàkíyèsí ilé eniyan burúkú, eniyan burúkú sì bọ́ sinu ìparun. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí igbe talaka, òun náà yóo kígbe, ṣugbọn kò ní rí ẹni dá a lóhùn. Ẹ̀bùn tí a fúnni ní kọ̀rọ̀ a máa paná ibinu, àbẹ̀tẹ́lẹ̀ tí a tì bọ abẹ́ aṣọ a máa paná ìjà. Tí a bá ṣe ìdájọ́ òtítọ́, inú olódodo a dùn, ṣugbọn ìfòyà ni fún àwọn aṣebi. Ẹni tí ó sá kúrò lọ́nà òye yóo sinmi láàrin àwọn òkú.
Owe 21:1-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ OLúWA; a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi. Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀ ṣùgbọ́n, OLúWA ló ń díwọ̀n ọkàn. Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí OLúWA ju ẹbọ lọ. Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga, ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni! Ètè àwọn olóye jásí èrè bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá. Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́ jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú. Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ, nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́. Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́. Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà. Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀. Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n, nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀. Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú, òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú; ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́. Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò: àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá, dẹ́kun ìbínú líle. Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́: ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀. Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye, yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.