Owe 16:1-16

Owe 16:1-16 Yoruba Bible (YCE)

Èrò ọkàn ni ti eniyan ṣugbọn OLUWA ló ni ìdáhùn. Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó mọ́ lójú ara rẹ̀, ṣugbọn OLUWA ló rí ọkàn. Fi gbogbo àdáwọ́lé rẹ lé OLUWA lọ́wọ́, èrò ọkàn rẹ yóo sì yọrí sí rere. OLUWA a máa jẹ́ kí ohun gbogbo yọrí sí bí ó bá ti fẹ́, ó dá eniyan burúkú fún ọjọ́ ìyọnu. OLUWA kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ agbéraga, dájúdájú kò ní lọ láìjìyà. Àánú ati òtítọ́ a máa ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀, ìbẹ̀rù OLUWA a sì máa mú ibi kúrò. Bí ọ̀nà eniyan bá tẹ́ OLUWA lọ́rùn, a máa mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ pàápàá bá a gbé pẹlu alaafia. Ìwọ̀nba ọrọ̀ pẹlu òdodo, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ tí a kójọ lọ́nà èrú lọ. Eniyan lè jókòó kí ó ṣètò ìgbésẹ̀ rẹ̀, ṣugbọn OLUWA níí tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni. Pẹlu ìmísí Ọlọrun ni ọba fi ń sọ̀rọ̀, ìdájọ́ aiṣododo kò gbọdọ̀ ti ẹnu rẹ̀ jáde. Ti OLUWA ni òṣùnwọ̀n pípé, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo ohun tí à ń wọ̀n. Àwọn ọba kórìíra ibi ṣíṣe, nítorí nípa òdodo ni a fìdí ìjọba múlẹ̀. Inú ọba a máa dùn sí olódodo, ọba sì máa ń fẹ́ràn àwọn tí ń sọ òtítọ́. Iranṣẹ ikú ni ibinu ọba, ọlọ́gbọ́n eniyan níí tù ú lójú. Ìyè wà ninu ojurere ọba, ojurere rẹ̀ sì dàbí ṣíṣú òjò ní àkókò òjò àkọ́rọ̀. Ó sàn kí eniyan ní òye ju kí ó ní wúrà lọ, ó sì sàn kí eniyan yan ìmọ̀ ju kí ó yan fadaka lọ.

Owe 16:1-16 Yoruba Bible (YCE)

Èrò ọkàn ni ti eniyan ṣugbọn OLUWA ló ni ìdáhùn. Gbogbo ọ̀nà eniyan ni ó mọ́ lójú ara rẹ̀, ṣugbọn OLUWA ló rí ọkàn. Fi gbogbo àdáwọ́lé rẹ lé OLUWA lọ́wọ́, èrò ọkàn rẹ yóo sì yọrí sí rere. OLUWA a máa jẹ́ kí ohun gbogbo yọrí sí bí ó bá ti fẹ́, ó dá eniyan burúkú fún ọjọ́ ìyọnu. OLUWA kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ agbéraga, dájúdájú kò ní lọ láìjìyà. Àánú ati òtítọ́ a máa ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀, ìbẹ̀rù OLUWA a sì máa mú ibi kúrò. Bí ọ̀nà eniyan bá tẹ́ OLUWA lọ́rùn, a máa mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ pàápàá bá a gbé pẹlu alaafia. Ìwọ̀nba ọrọ̀ pẹlu òdodo, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ tí a kójọ lọ́nà èrú lọ. Eniyan lè jókòó kí ó ṣètò ìgbésẹ̀ rẹ̀, ṣugbọn OLUWA níí tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni. Pẹlu ìmísí Ọlọrun ni ọba fi ń sọ̀rọ̀, ìdájọ́ aiṣododo kò gbọdọ̀ ti ẹnu rẹ̀ jáde. Ti OLUWA ni òṣùnwọ̀n pípé, iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo ohun tí à ń wọ̀n. Àwọn ọba kórìíra ibi ṣíṣe, nítorí nípa òdodo ni a fìdí ìjọba múlẹ̀. Inú ọba a máa dùn sí olódodo, ọba sì máa ń fẹ́ràn àwọn tí ń sọ òtítọ́. Iranṣẹ ikú ni ibinu ọba, ọlọ́gbọ́n eniyan níí tù ú lójú. Ìyè wà ninu ojurere ọba, ojurere rẹ̀ sì dàbí ṣíṣú òjò ní àkókò òjò àkọ́rọ̀. Ó sàn kí eniyan ní òye ju kí ó ní wúrà lọ, ó sì sàn kí eniyan yan ìmọ̀ ju kí ó yan fadaka lọ.

Owe 16:1-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)

Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ OLúWA ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá. Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n OLúWA ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn. Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé OLúWA lọ́wọ́ Èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe. OLúWA ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú. OLúWA kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà. Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù OLúWA ènìyàn sá fún ibi. Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ OLúWA lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà. Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ. Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n OLúWA ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀. Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké. Òdínwọ̀n àti òṣùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ OLúWA; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀. Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀. Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́. Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú. Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò. Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!