Owe 15:20-33
Owe 15:20-33 Bibeli Mimọ (YBCV)
Ọlọgbọ́n ọmọ ṣe ayọ̀ baba; ṣugbọn aṣiwère enia gàn iya rẹ̀. Ayọ̀ ni wère fun ẹniti oye kù fun; ṣugbọn ẹni-oye a ma rìn ni iduroṣinṣin. Laisi ìgbimọ, èro a dasan; ṣugbọn li ọ̀pọlọpọ ìgbimọ, nwọn a fi idi mulẹ. Enia ni ayọ̀ nipa idahùn ẹnu rẹ̀; ati ọ̀rọ kan li akoko rẹ̀, o ti wọ̀ to? Ọ̀na ìye lọ soke fun ọlọgbọ́n, ki o le kuro ni ipo-okú nisalẹ. Oluwa yio run ile agberaga; ṣugbọn yio fi ìpãlà opó kalẹ. Ìro inu enia buburu, irira ni loju Oluwa; ṣugbọn mimọ́ ni ọ̀rọ didùn niwaju rẹ̀. Ẹniti o njẹ ère aiṣododo, o nyọ ile ara rẹ̀ lẹnu; ṣugbọn ẹniti o korira ẹ̀bun yio yè. Aiya olododo ṣe àṣaro lati dahùn; ṣugbọn ẹnu enia buburu ngufẹ ohun ibi jade. Oluwa jina si awọn enia-buburu; ṣugbọn o gbọ́ adura awọn olododo. Imọlẹ oju mu inu dùn; ihin rere si mu egungun sanra. Ẹniti o ba gbọ́ ibawi ìye, a joko lãrin awọn ọlọgbọ́n. Ẹniti o kọ̀ ẹkọ́, o gàn ọkàn ara rẹ̀: ṣugbọn ẹniti o ba gbọ́ ibawi, o ni imoye. Ibẹ̀ru Oluwa li ẹkọ́ ọgbọ́n; ati ṣãju ọlá ni irẹlẹ.
Owe 15:20-33 Yoruba Bible (YCE)
Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣugbọn òmùgọ̀ ọmọ níí kẹ́gàn ìyá rẹ̀. Ayọ̀ ni ìwà òmùgọ̀ jẹ́ fún aláìgbọ́n, ṣugbọn ẹni tí ó ní òye a máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́. Àìsí ìmọ̀ràn a máa mú kí ètò dàrú, ṣugbọn ọpọlọpọ ìmọ̀ràn a máa mú kí ó yọrí sí rere. Ìdáhùn kíkún a máa fúnni láyọ̀, kí ọ̀rọ̀ bọ́ sí àsìkò dára lọpọlọpọ! Ọ̀nà ọlọ́gbọ́n lọ tààrà sinu ìyè, kí ó má baà bọ́ sinu isà òkú. OLUWA a máa wó ilé agbéraga, ṣugbọn ó ṣe àmójútó ààlà opó. Ohun ìríra ni èrò ọkàn ẹni ibi lójú OLUWA, ṣugbọn ọrọ̀ àwọn ẹni mímọ́ jẹ́ dídùn inú rẹ̀. Àwọn tí ń ṣojúkòkòrò èrè àìtọ́ ń kó ìyọnu bá ilé wọn, ṣugbọn àwọn tí wọn kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóo yè. Olódodo a máa ronú kí ó tó fèsì ọ̀rọ̀, ṣugbọn ọ̀rọ̀ burúkú níí máa jáde lẹ́nu àwọn eniyan burúkú. OLUWA jìnnà sí eniyan burúkú, ṣugbọn a máa gbọ́ adura olódodo. Ọ̀yàyà a máa mú inú dùn, ìròyìn ayọ̀ a sì máa mú ara yá. Ẹni tó gbọ́ ìbáwí rere yóo wà láàrin àwọn ọlọ́gbọ́n. Ẹni tí kò náání ìbáwí tàbùkù ara rẹ̀, ṣugbọn ẹni tí ó bá gba ìmọ̀ràn yóo ní òye. Ìbẹ̀rù OLUWA níí kọ́ni lọ́gbọ́n, ìwà ìrẹ̀lẹ̀ níí ṣáájú iyì.
Owe 15:20-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ọlọ́gbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aṣiwèrè ènìyàn kẹ́gàn ìyá rẹ̀. Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀; ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà. Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn; ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn wà. Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó yẹ ọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀! Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọ́gbọ́n láti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú. OLúWA fa ilé onígbèéraga ya lulẹ̀, ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó onírẹ̀lẹ̀ mọ́ láìyẹ̀. OLúWA kórìíra èrò ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n mímọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹni pípé. Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè. Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò ṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde. OLúWA jìnnà sí ènìyàn búburú ṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo. Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn, ìròyìn ayọ̀ sì ń mú ìlera wá sínú egungun. Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè, yóò wà ní àpéjọpọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n. Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀, Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí yóò ní ìmọ̀ sí i. Ìbẹ̀rù OLúWA kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n, Ìrẹ̀lẹ̀ sì ni ó máa ń ṣáájú ọlá.