Isa 56:1-2
Isa 56:1-2 Bibeli Mimọ (YBCV)
BAYI li Oluwa wi, Ẹ pa idajọ mọ, ẹ si ṣe ododo: nitori igbala mi fẹrẹ idé, ati ododo mi lati fi hàn. Alabukun ni fun ọkunrin na ti o ṣe eyi, ati fun ọmọ enia ti o dì i mu: ti o pa ọjọ isimi mọ laisọ ọ di aimọ́; ti o si pa ọwọ́ rẹ̀ mọ kuro ni ṣiṣe ibi.
Isa 56:1-2 Yoruba Bible (YCE)
OLUWA ní: “Ẹ máa dá ẹjọ́ ẹ̀tọ́, kí ẹ sì máa ṣe òdodo; nítorí ìgbàlà mi yóo dé láìpẹ́, ẹ óo sì rí ìdáǹdè mi. Ayọ̀ ń bẹ fún gbogbo ẹni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ati fún ẹni tí ó bá ń tẹ̀lé e, tí ó ń ṣọ́ra, tí kò rú òfin ọjọ́ ìsinmi, tí kò sì fi ọwọ́ rẹ̀ ṣe nǹkan burúkú.”
Isa 56:1-2 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Èyí ni ohun ti OLúWA sọ: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ. Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”