Isa 32:1-8
Isa 32:1-8 Bibeli Mimọ (YBCV)
KIYESI i, ọba kan yio jẹ li ododo, awọn olori yio fi idajọ ṣe akoso. Ẹnikan yio si jẹ bi ibi isápamọ́ kuro loju ẹfũfu, ati ãbo kuro lọwọ ijì; bi odo-omi ni ibi gbigbẹ, bi ojiji apata nla ni ilẹ gbigbẹ. Oju awọn ẹniti o riran kì yio ṣe baibai, ati eti awọn ti o ngbọ́ yio tẹ́ silẹ. Ọkàn awọn oniwàduwàdu yio mọ̀ oye, ahọn awọn akolòlo yio sọ̀rọ kedere. A kì yio tun pè alaigbọ́n ni ẹni-ọlá mọ, bẹ̃ni a kì yio pe ọ̀bàlújẹ́ ni ẹni pataki mọ. Nitori eniakenia yio ma sọ isọkusọ, ọkàn rẹ̀ yio si ma ṣiṣẹ aiṣedede, lati ṣe agabàgebe, ati lati ṣì ọ̀rọ sọ si Oluwa, lati sọ ọkàn ẹniti ebi npa di ofo, ati lati mu ki ohun-mimu awọn ti ongbẹ ngbẹ ki o dá. Ibi ni gbogbo ohun-elò enia-kenia jẹ pẹlu: on gbà èro buburu, lati fi ọ̀rọ eke pa talaka run, bi alaini tilẹ nsọ õtọ ọ̀rọ. Ṣugbọn ẹni-rere a ma gbèro ohun rere; nipa ohun-rere ni yio ṣe duro.
Isa 32:1-8 Yoruba Bible (YCE)
Wò ó! Ọba kan yóo jẹ pẹlu òdodo, àwọn ìjòyè yóo sì máa ṣe àkóso pẹlu ẹ̀tọ́. Olukuluku yóo dàbí ibi ààbò nígbà tí ẹ̀fúùfù bá ń fẹ́ ati ibi ìsásí nígbà tí ìjì bá ń jà Wọ́n óo dàbí odò ninu aṣálẹ̀, ati bí ìbòòji àpáta ńlá nílẹ̀ olóoru. Àwọn tí wọ́n bá rí i kò ní dijú sí i, etí àwọn tí ó gbọ́ ọ kò ní di. Àwọn tí kò ní àròjinlẹ̀ tẹ́lẹ̀ yóo ní òye, àwọn akólòlò yóo sì sọ̀rọ̀ ketekete. A kò ní máa pe aláìgbọ́n ní ọlọ́lá mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní máa pe abàlújẹ́ ní eniyan pataki. Nítorí pé aláìgbọ́n ń sọ̀rọ̀ òmùgọ̀, ọkàn rẹ̀ sì ń pète ibi. Ó ń ro bí yóo ṣe hùwà ẹni tí kò mọ Ọlọrun, tí yóo sọ̀rọ̀ ìsọkúsọ sí OLUWA; tí yóo fi ẹni tí ebi ń pa sílẹ̀, láì fún un ní oúnjẹ, tí yóo sì fi omi du ẹni òùngbẹ ń gbẹ. Kìkì ibi ni èrò inú àwọn eniyankeniyan. Wọn a máa pète ìkà, láti fi irọ́ pa àwọn talaka run, kì báà jẹ́ pé ẹjọ́ aláìní jàre. Ṣugbọn eniyan rere a máa ro èrò rere, ìdí nǹkan rere ni à á sì í bá wọn.
Isa 32:1-8 Bibeli Mimọ (YBCV)
KIYESI i, ọba kan yio jẹ li ododo, awọn olori yio fi idajọ ṣe akoso. Ẹnikan yio si jẹ bi ibi isápamọ́ kuro loju ẹfũfu, ati ãbo kuro lọwọ ijì; bi odo-omi ni ibi gbigbẹ, bi ojiji apata nla ni ilẹ gbigbẹ. Oju awọn ẹniti o riran kì yio ṣe baibai, ati eti awọn ti o ngbọ́ yio tẹ́ silẹ. Ọkàn awọn oniwàduwàdu yio mọ̀ oye, ahọn awọn akolòlo yio sọ̀rọ kedere. A kì yio tun pè alaigbọ́n ni ẹni-ọlá mọ, bẹ̃ni a kì yio pe ọ̀bàlújẹ́ ni ẹni pataki mọ. Nitori eniakenia yio ma sọ isọkusọ, ọkàn rẹ̀ yio si ma ṣiṣẹ aiṣedede, lati ṣe agabàgebe, ati lati ṣì ọ̀rọ sọ si Oluwa, lati sọ ọkàn ẹniti ebi npa di ofo, ati lati mu ki ohun-mimu awọn ti ongbẹ ngbẹ ki o dá. Ibi ni gbogbo ohun-elò enia-kenia jẹ pẹlu: on gbà èro buburu, lati fi ọ̀rọ eke pa talaka run, bi alaini tilẹ nsọ õtọ ọ̀rọ. Ṣugbọn ẹni-rere a ma gbèro ohun rere; nipa ohun-rere ni yio ṣe duro.
Isa 32:1-8 Yoruba Bible (YCE)
Wò ó! Ọba kan yóo jẹ pẹlu òdodo, àwọn ìjòyè yóo sì máa ṣe àkóso pẹlu ẹ̀tọ́. Olukuluku yóo dàbí ibi ààbò nígbà tí ẹ̀fúùfù bá ń fẹ́ ati ibi ìsásí nígbà tí ìjì bá ń jà Wọ́n óo dàbí odò ninu aṣálẹ̀, ati bí ìbòòji àpáta ńlá nílẹ̀ olóoru. Àwọn tí wọ́n bá rí i kò ní dijú sí i, etí àwọn tí ó gbọ́ ọ kò ní di. Àwọn tí kò ní àròjinlẹ̀ tẹ́lẹ̀ yóo ní òye, àwọn akólòlò yóo sì sọ̀rọ̀ ketekete. A kò ní máa pe aláìgbọ́n ní ọlọ́lá mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní máa pe abàlújẹ́ ní eniyan pataki. Nítorí pé aláìgbọ́n ń sọ̀rọ̀ òmùgọ̀, ọkàn rẹ̀ sì ń pète ibi. Ó ń ro bí yóo ṣe hùwà ẹni tí kò mọ Ọlọrun, tí yóo sọ̀rọ̀ ìsọkúsọ sí OLUWA; tí yóo fi ẹni tí ebi ń pa sílẹ̀, láì fún un ní oúnjẹ, tí yóo sì fi omi du ẹni òùngbẹ ń gbẹ. Kìkì ibi ni èrò inú àwọn eniyankeniyan. Wọn a máa pète ìkà, láti fi irọ́ pa àwọn talaka run, kì báà jẹ́ pé ẹjọ́ aláìní jàre. Ṣugbọn eniyan rere a máa ro èrò rere, ìdí nǹkan rere ni à á sì í bá wọn.
Isa 32:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Wò ó, ọba kan yóò jẹ nínú òdodo àwọn olórí yóò máa fi ìdájọ́ ṣe àkóso. Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò jẹ́ bí ibi ìṣápamọ́ kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ àti ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì, gẹ́gẹ́ bí odò omi ní ilẹ̀ aṣálẹ̀, àti bí òjìji àpáta ńlá ní ilẹ̀ gbígbẹ. Nígbà náà ni ojú àwọn tí ó rí kò ní padé mọ́, àti etí àwọn tí ó gbọ́ yóò tẹ́tí sílẹ̀. Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè, àti ahọ́n tí ń kólòlò ni yóò là geerege. A kò ní pe òmùgọ̀ ní ọlọ́lá mọ́ tàbí kí a fi ọ̀wọ̀ tí ó ga jù fún aláìlóòótọ́ ènìyàn. Nítorí òmùgọ̀ sọ̀rọ̀ òmùgọ̀, ọkàn rẹ̀ kún fún ìwà ibi: òun hùwà àìwà-bí-Ọlọ́run ó sì ń tan àṣìṣe tí ó kan OLúWA kalẹ̀; ẹni ebi ń pa ló fi sílẹ̀ lófo àti fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ ni ó mú omi kúrò. Ibi ni gbogbo ọgbọ́n àwọn ìkà ènìyàn jẹ́, ó ń gba èrò búburú láti fi ọ̀rọ̀ èké pa tálákà run, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀bẹ̀ aláìní sì tọ̀nà. Ṣùgbọ́n ọlọ́lá ènìyàn a máa pète ohun ńlá àti nípa èrò rere ni yóò dúró.