OLúWA ń jẹ ọba, ọláńlá ni ó wọ̀ ní aṣọ; ọláńlá ni OLúWA wọ̀ ní aṣọ àti ìhámọ́ra rẹ̀ pẹ̀lú agbára. Ó fi ìdí ayé múlẹ̀; kò sì le è yí. Ìjọba rẹ̀ wà láti ọjọ́ pípẹ́; ìwọ wà títí ayérayé. A ti gbé Òkun sókè, OLúWA, Òkun ti gbé ohùn wọn sókè; Òkun ti gbé rírú omi wọn sókè. Ó ni ògo ju àrá omi ńlá lọ, ó ni ògo ju Òkun rírú lọ OLúWA ga ní ògo. Ẹ̀rí rẹ̀ dúró ṣinṣin; ìwà mímọ́ ni ó fi ṣe ilé rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ fún ọjọ́ àìlópin, OLúWA.
Kà Saamu 93
Feti si Saamu 93
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Saamu 93:1-5
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò