Saamu 86:1-17

Saamu 86:1-17 YCB

Gbọ́, OLúWA, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní. Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ. Ṣàánú fún mi, OLúWA, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́. Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, OLúWA, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí. Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, OLúWA, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́, Gbọ́ àdúrà mi, OLúWA; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú. Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn. Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, OLúWA: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá, láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, OLúWA; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run. Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, OLúWA, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè. Ṣùgbọ́n ìwọ, OLúWA, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́. Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là. Fi ààmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ OLúWA ni ó ti tù mí nínú.