Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run; Àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́; wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́. Kò sí ohùn tàbí èdè níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé, ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé. Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run. Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá, òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje. Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀; kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀. Pípé ni òfin OLúWA, ó ń yí ọkàn padà. Ẹ̀rí OLúWA dánilójú, ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n. Ìlànà OLúWA tọ̀nà, ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn. Àṣẹ OLúWA ni mímọ́, ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú. Ìbẹ̀rù OLúWA mọ́, ó ń faradà títí láéláé. Ìdájọ́ OLúWA dájú òdodo ni gbogbo wọn. Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ, ju wúrà tí o dára jùlọ, wọ́n dùn ju oyin lọ, àti ju afárá oyin lọ.
Kà Saamu 19
Feti si Saamu 19
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Saamu 19:1-10
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò