Ẹ fi ìyìn fún OLúWA. Fi ìyìn fún OLúWA, ìwọ ọkàn mi. Èmi yóò yin OLúWA ní gbogbo ayé mi; Èmi yóò kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láààyè. Ẹ má ṣe ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú àwọn ọmọ-aládé, àní, ọmọ ènìyàn, lọ́wọ́ ẹni tí kò sí ìrànlọ́wọ́. Ẹ̀mí rẹ jáde lọ, ó padà sí erùpẹ̀: Ní ọjọ́ náà gan, èrò wọn yóò di òfo: Ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run Jakọbu ń ṣe ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ tí ìrètí rẹ̀ wà nínú OLúWA Ọlọ́run rẹ̀. Ẹni tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ẹni tí ó pa òtítọ́ mọ́ títí ayé. Ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí a ni lára tí ó fi oúnjẹ fún àwọn tí ebi ń pa OLúWA, tú àwọn oǹdè sílẹ̀ (ẹlẹ́wọ̀n) OLúWA mú àwọn afọ́jú ríran, OLúWA, gbé àwọn tí a rẹ̀ sílẹ̀ ga, OLúWA fẹ́ràn àwọn olódodo. OLúWA ń dá ààbò bo àwọn àlejò ó sì ń dá àwọn aláìní baba àti opó sí ṣùgbọ́n ó ba ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú jẹ́. OLúWA jẹ ọba títí láé; Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni, àti fún gbogbo ìran.
Kà Saamu 146
Feti si Saamu 146
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Saamu 146:1-10
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò