Malaki 3:16-17

Malaki 3:16-17 YCB

Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù OLúWA ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, OLúWA sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù OLúWA, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀. “Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni OLúWA àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.