Nítorí náà lẹ́yìn tí ó wẹ ẹsẹ̀ wọn tán, tí ó sì ti mú agbádá rẹ̀, tí ó tún jókòó, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ ohun tí mo ṣe sí yín bí? Ẹ̀yin ń pè mí ní ‘Olùkọ́’ àti ‘Olúwa,’ ẹ̀yin wí rere; bẹ́ẹ̀ ni mo jẹ́. Ǹjẹ́ bí èmi tí í ṣe Olúwa àti olùkọ́ yín bá wẹ ẹsẹ̀ yín, ó tọ́ kí ẹ̀yin pẹ̀lú sì máa wẹ ẹsẹ̀ ara yín. Nítorí mo fi àpẹẹrẹ fún yín, kí ẹ̀yin lè máa ṣe gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí yín. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọmọ ọ̀dọ̀ kò tóbi ju ọ̀gá rẹ̀ lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí a rán kò tóbi ju ẹni tí ó rán an lọ. Bí ẹ̀yin bá mọ nǹkan wọ̀nyí, alábùkún fún ni yín, bí ẹ̀yin bá ń ṣe wọ́n! “Kì í ṣe ti gbogbo yín ni mo ń sọ: èmi mọ àwọn tí mo yàn: ṣùgbọ́n kí Ìwé mímọ́ bá à lè ṣẹ, ‘ẹni tí ń bá mi jẹun pọ̀ sì gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sí mi.’
Kà Johanu 13
Feti si Johanu 13
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: Johanu 13:12-18
3 Awọn ọjọ
Ìdarí jẹ́ ọ̀kan láti àwọn ìkànnì tí Ọlọ́run máa ń lò láti pèsè àwọn ènìyàn Rẹ̀ sílẹ̀ fún ìgbésí-ayé àti iṣẹ̀-ńlá ti ìjọba rẹ̀. Àwọn èrèdí máa ń já gaara sí i, àwọn ìrìn-àjò máa dán mọ́nrán sí i láyé pẹ̀lú ìdarí tó tọ̀nà. Nítorí náà, Ọlọ́run ń mọ̀ọ́mọ̀ pe, ó sì ń fi agbára fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n máa mú ìpè ńlá yìí sẹ.
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò