Ìṣe àwọn Aposteli Ìfáàrà

Ìfáàrà
Ẹni tó kọ ìwé yìí kò dárúkọ ara rẹ̀, ṣùgbọ́n a lè ti ipa ohun tí a rí kà tọ́ka sí Luku gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó kọ ọ́. Ìwé yìí jẹ́ ìtẹ̀síwájú ìhìnrere Luku níbi tí Luku ti fi yé wa pé ohun tí Jesu bẹ̀rẹ̀ nínú ayé náà ni ó ń ṣe nínú ìgbé ayé àwọn ọmọ Ọlọ́run. Ìṣẹ̀lẹ̀ inú ìwé yìí bẹ̀rẹ̀ níbi tí àwọn aposteli ti kún fún agbára Ọlọ́run àti ìwàásù tó so èso púpọ̀, ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn ni a gbà lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ ní ọjọ́ kan (2.41). Ìgbé ayé ilé Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, ìtànkálẹ̀ ìhìnrere ní Samaria, iṣẹ́ ìhìnrere aposteli Peteru àti bí inúnibíni sí àwọn onígbàgbọ́ ṣe bẹ̀rẹ̀ ni a ṣe àpèjúwe. Àkíyèsí wa darí sí orí aposteli Paulu àti iṣẹ́ ìhìnrere rẹ̀ ní àwọn ilẹ̀ tí kì í ṣe Júù. Ìrìnàjò iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ni ó ní àkọsílẹ̀ kíkún, èyí tó parí pẹ̀lú ìrìnàjò rẹ sí Romu níbi tí ìwé náà parí sí.
A kọ ìwé Ìṣe àwọn Aposteli láti fi ṣe àfihàn ìtànkálẹ̀ iṣẹ́ ìhìnrere láti ọ̀dọ̀ àwọn Júù dé ilẹ̀ àwọn tí kì í ṣe Júù (1.8). Ìròyìn ayọ̀ pé Jesu kú, ó sì jí dìde yóò di mí mọ̀ ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé. Ọlọ́run gbé agbára wọ àwọn ènìyàn rẹ̀ kí wọn ba à lè ṣe iṣẹ́ wọn ní àṣeyọrí. Ẹ̀mí Mímọ́ ni agbára náà. Ọwọ́ agbára ńlá Ọlọ́run hàn lórí ohun gbogbo, èyí tó mú iṣẹ́ ìhìnrere borí ìbọ̀rìṣà àti inúnibíni. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ni yóò torí èyí jẹ ìyà púpọ̀, ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Peteru àti Paulu nínú Ìṣe àwọn Aposteli jẹ́ àpẹẹrẹ ìṣẹ́gun tó dájú ni a ṣe ìlérí láti ipasẹ̀ Jesu Ọlọ́run wa.
Kókó-ọ̀rọ̀
i. Ìjọ Ọlọ́run ní ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ wá 1.1–5.42.
ii. Inúnibíni àti ìtẹ̀síwájú ìhìnrere 6.1–9.32.
iii. Iṣẹ́ ìránṣẹ́ Peteru 9.32–12.25.
iv. Ìrìnàjò Paulu kìn-ín-ní 13.1–14.28.
v. Àjọ ìgbìmọ̀ Jerusalẹmu 15.1-41.
vi. Ìrìnàjò Paulu kejì 16.1–18.22.
vii. Ìrìnàjò Paulu kẹta 18.23–21.14.
viii. Fífi àṣẹ ọba mú Paulu àti ìrìnàjò lọ sí Romu 21.15–28.31.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

Ìṣe àwọn Aposteli Ìfáàrà: YCB

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀