Hab Ọ̀rọ̀ Iṣaaju

Ọ̀rọ̀ Iṣaaju
Ní nǹkan bíi ẹgbẹta ọdún ó lé díẹ̀ kí á tó bí OLUWA wa, (7th Century B.C.), ni wolii Habakuku sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, orílẹ̀-èdè Babilonia ni aláṣẹ lórí gbogbo orílẹ̀-èdè yòókù ní gbogbo àkókò yìí. Ìwà ipá tí àwọn aláṣẹ ìgbà náà ń hù sí àwọn ọmọ Israẹli ní pataki jẹ́ ẹ̀dùn ọkàn wolii Habakuku. Ó wá bèèrè lọ́wọ́ OLUWA ìdí tí OLUWA fi dákẹ́ tí àwọn aláṣẹ wọnyi sì ń pa àwọn tí wọ́n ṣe olódodo jù wọ́n lọ. (1:13) Èsì tí OLUWA fún un ni pé, àkókò tí ó bá tọ́ lójú òun ni òun yóo gbé ìgbésẹ̀ tí ó bá yẹ, ṣugbọn sibẹ, “àwọn olódodo yóo wà láàyè nípa igbagbọ.” (2:4)
Ìyókù orí keji ìwé yìí ń sọ nípa ìparun tí yóo dé bá àwọn alaiṣododo. Orin ni Habakuku fi parí ọ̀rọ̀ rẹ̀. Orin ọ̀hún sọ nípa títóbi Ọlọrun, ó sì fi ẹ̀mí igbagbọ tí kì í ṣákì, tí ẹni tí ó kọ ọ́ ní hàn.
Àwọn Ohun tí ó wà ninu Ìwé yìí ní Ìsọ̀rí-ìsọ̀rí
Àwọn ẹ̀sùn Habakuku ati àwọn èsì tí OLUWA fún un 1:1—2:4
Ìparun tí yóo bá àwọn alaigbagbọ 2:5-20
Adura Habakuku 3:1-19

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

Hab Ọ̀rọ̀ Iṣaaju: YBCV

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀