Saulu si jọba lori Israeli; o si bá gbogbo awọn ọta rẹ̀ jà yika, eyini ni Moabu ati awọn ọmọ Ammoni, ati Edomu, ati awọn ọba Soba ati awọn Filistini: ati ibikibi ti o yi si, a bà wọn ninu jẹ. O si ko ogun jọ, o si kọlu awọn Amaleki, o si gbà Israeli silẹ lọwọ awọn ti o nkó wọn. Awọn ọmọ Saulu si ni Jonatani, ati Iṣui, ati Malkiṣua; ati orukọ ọmọbinrin rẹ̀ mejeji si ni wọnyi; orukọ akọbi ni Merabu, ati orukọ aburo ni Mikali: Ati orukọ aya Saulu ni Ahinoamu, ọmọbinrin Ahimaasi, ati orukọ olori ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arakunrin baba Saulu. Kiṣi si ni baba Saulu; ati Neri ni baba Abneri ọmọ Abieli. Ogun na si le si awọn Filistini ni gbogbo ọjọ Saulu: bi Saulu ba ri ẹnikan ti o li agbara, tabi akikanju ọkunrin, a mu u sọdọ rẹ̀.
Kà I. Sam 14
Feti si I. Sam 14
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: I. Sam 14:47-52
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò