OLUWA jọba; ó gbé ọlá ńlá wọ̀ bí ẹ̀wù; OLUWA gbé ọlá ńlá wọ̀, ó sì di agbára ni àmùrè. Ó fi ìdí ayé múlẹ̀; kò sì ní yẹ̀ laelae. A ti fi ìdí ìjọba rẹ múlẹ̀ láti ìgbà laelae; láti ayérayé ni o ti wà. Ibú omi gbé ohùn wọn sókè, OLUWA, ibú omi gbé ohùn wọn sókè, ó sì ń sán bí ààrá. OLUWA lágbára lókè! Ó lágbára ju ariwo omi òkun lọ, ó lágbára ju ìgbì omi òkun lọ. Àwọn òfin rẹ kìí yipada, ìwà mímọ́ ni ó yẹ ilé rẹ títí lae, OLUWA.
Kà ORIN DAFIDI 93
Pín
Fi gbogbo Èyá wéra: ORIN DAFIDI 93:1-5
Ṣe àfipamọ́ àwọn ẹsẹ, kàá ní aìsìní orí ayélujára, wo àwọn àgékúrú ìkọ́ni, àti díẹ̀ síi!
Ilé
Bíbélì
Àwon ètò
Àwon Fídíò