ORIN DAFIDI 21

21
Orin Ìṣẹ́gun
1Ọba ń yọ̀ nítorí agbára rẹ, OLUWA;
inú rẹ̀ ń dùn lọpọlọpọ nítorí ríràn tí o ràn án lọ́wọ́!
2O ti fún un ní ohun tí ọkàn rẹ̀ ń fẹ́,
o kò sì fi ohun tí ó ń tọrọ dù ú.
3O gbé ibukun dáradára pàdé rẹ̀;
o fi adé ojúlówó wúrà dé e lórí.
4Ó bèèrè ẹ̀mí gígùn lọ́wọ́ rẹ; o fi fún un,
àní, ọjọ́ gbọọrọ títí ayé.
5Òkìkí rẹ̀ pọ̀ nítorí pé o ràn án lọ́wọ́;
o sì fi iyì ati ọlá ńlá jíǹkí rẹ̀.
6Nítòótọ́ o sọ ọ́ di ẹni ibukun títí lae;
o sì mú kí inú rẹ̀ dùn nítorí pé o wà pẹlu rẹ̀.
7Nítorí pé ọba gbẹ́kẹ̀lé OLUWA;
a kò ní ṣí i ní ipò pada,
nítorí ìfẹ́ Ọ̀gá Ògo tí kì í yẹ̀.
8Ọwọ́ rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ;
ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóo tẹ gbogbo àwọn tí ó kórìíra rẹ.
9O óo jó wọn run bí iná ìléru, nígbà tí o bá yọ sí wọn.
OLUWA yóo gbé wọn mì ninu ibinu rẹ̀;
iná yóo sì jó wọn ní àjórun.
10O óo pa àwọn ọmọ wọn run lórí ilẹ̀ ayé,
o óo sì run ìran wọn láàrin àwọn eniyan.
11Bí wọn bá gbèrò ibi sí ọ,
tí wọ́n sì pète ìkà, wọn kò ní lè ṣe é.
12Nítorí pé o óo lé wọn sá;
nígbà tí o bá fi ọfà rẹ sun ojú wọn.
13A gbé ọ ga, nítorí agbára rẹ, OLUWA!
A óo máa kọrin, a óo sì máa yin agbára rẹ.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 21: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa