ORIN DAFIDI 19

19
Ògo Ọlọrun ninu àwọn ohun tí Ó dá
1Ojú ọ̀run ń sọ̀rọ̀ ògo Ọlọrun,
òfuurufú sì ń kéde iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
2Ọjọ́ dé ọjọ́ ń sọ ọ́ ní àsọgbà
òru dé òru sì ń fi ìmọ̀ rẹ̀ hàn.
3Wọn kò fọ èdè kankan, wọn kò sì sọ ọ̀rọ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò gbọ́ ohùn wọn;
4sibẹ ìró wọn la gbogbo ayé já,
ọ̀rọ̀ wọn sì dé òpin ayé.
Ó pàgọ́ fún oòrùn lójú ọ̀run,
5tí ó ń yọ jáde bí ọkọ iyawo tí ń jáde láti inú yàrá rẹ̀,
ati bí akọni tí ara ń wá láti fi tayọ̀tayọ̀ sáré ìje.
6Láti apá kan ojú ọ̀run ni ó ti ń yọ wá,
a máa yípo gbogbo ojú ọ̀run dé apá keji;
kò sì sí ohun tí ó bọ́ lọ́wọ́ ooru rẹ̀.#Rom 10:18
Òfin OLUWA
7Òfin OLUWA pé, a máa sọ ọkàn jí;
àṣẹ OLUWA dájú, ó ń sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.
8Ìlànà OLUWA tọ́, ó ń mú ọkàn yọ̀,
àṣẹ OLUWA péye, a máa lani lójú.
9Ìbẹ̀rù OLUWA pé, ó wà títí lae,
ìdájọ́ OLUWA tọ́, òdodo ni gbogbo wọn.
10Wọ́n wuni ju wúrà lọ,
àní ju ojúlówó wúrà lọ;
wọ́n sì dùn ju oyin,
àní, wọ́n dùn ju oyin tí ń kán láti inú afárá lọ.
11Pẹlupẹlu àwọn ni wọ́n ń ki èmi iranṣẹ rẹ, nílọ̀,
èrè pupọ sì ń bẹ ninu pípa wọ́n mọ́.
12Ṣugbọn ta ni lè mọ àṣìṣe ara rẹ̀?
Wẹ̀ mí mọ́ ninu àṣìṣe àìmọ̀ mi.
13Pa èmi iranṣẹ rẹ mọ́ kúrò ninu ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀-ọ́n-mọ̀-dá;
má jẹ́ kí wọ́n jọba lórí mi.
Nígbà náà ni ara mi yóo mọ́,
n kò sì ní jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
14Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ati àṣàrò ọkàn mi
jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ,
OLUWA ibi ààbò mi ati olùràpadà mi.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

ORIN DAFIDI 19: YCE

Ìsàmì-sí

Pín

Daako

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀

YouVersion nlo awọn kuki lati ṣe adani iriri rẹ. Nipa lilo oju opo wẹẹbu wa, o gba lilo awọn kuki wa gẹgẹbi a ti ṣalaye ninu Eto Afihan wa